Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 24:16-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Kí a má ri tí àwa yóò fi kọ Olúwa sílẹ̀ láti sin òrìṣà.!

17. Nítorí Olúwa Ọlọ́run fúnrarẹ̀ ni ó gba àwọn baba ńlá wa là kúrò ní Éjíbítì, ní oko ẹrú. Òun ni Ọlọ́run tí ó ṣe ìyanu ńlá níwájú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì. Ó pa wá mọ́ nínú gbogbo ìrìnàjò wa àti ní àárin gbogbo orílẹ̀ èdè tí a là kọjá.

18. Olúwa sì lé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè jáde kúrò ní iwájú wa, pẹ̀lú àwọn Ámórì, tí ń gbé ilẹ̀ náà. Àwa náà yóò máa sin Olúwa, nítorí òun ni Ọlọ́run wa.”

19. Jóṣúà sì wí fún àwọn ènìyàn náà, pé, “Ẹ̀yin kò le sin Olúwa, nítorí Ọlọ́run mímọ́ ni òun; Ọlọ́run owú ni òun, Kì yóò dárí ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín.

20. Bí ẹ bá kọ Olúwa tí ẹ sì sin òrìṣà orílẹ̀ èdè mìíràn òun yóò padà yóò sì mú ibi bá a yín, yóò sì pa yín run, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣe rere fún un yín tan.”

21. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn sọ fún Jóṣúà pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! A yàn láti sin Olúwa.”

22. Lẹ́yìn náà ni Jóṣúà wí pé, “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ara yín pé, ẹ ti yàn láti sin Olúwa.”Wọ́n dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí.”

23. Nígbà náà ni Jóṣúà dáhùn wí pé, “Ẹ mú òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn tí ń bẹ ní àárin yín kúrò, ki ẹ sì yí ọkàn yín padà sí Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì.”

24. Àwọn ènìyàn náà sì wí fún Jóṣúà pé, “Olúwa Ọlọ́run nìkan ni àwa yóò máa sìn, òun nìkan ni àwa yóò máa ṣe ìgbọràn sí.”

25. Ní ọjọ́ náà Jóṣúà dá májẹ̀mu fún àwọn ènìyàn, ó sì fi òfin àti ìlànà fún wọn ní Sékémù.

26. Jóṣúà sì kọ gbogbo ìdàhùn àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí inú Ìwé Òfin Ọlọ́run. Lẹ́yìn náà ó gbé òkúta ńlá kan, ó gbé e kalẹ̀ ní abẹ́ igi Óákù ní ẹ̀bá ibi-mímọ́ Olúwa.

27. “E wò ó!” ó wí fún gbogbo ènìyàn pé, “Òkúta yìí ni yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí fún wa, nítorí ó ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ fún wa. Yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí yín tí ẹ bá ṣe àìṣòtítọ́ sí Ọlọ́run yín.”

28. Lẹ́yìn náà ni Jóṣúà jẹ́ kí àwọn ènìyàn lọ, olúkúlùkù sí ilẹ̀-ìní rẹ̀,

Ka pipe ipin Jóṣúà 24