Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 10:33-39 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

33. Ní àkókò yìí, Hórámì ọba Gésérì gòkè láti ran Lákíṣì lọ́wọ́, ṣùgbọ́n Jóṣúà ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ ogun rẹ̀ títí ti kò fi ku ẹnìkan sílẹ̀.

34. Nígbà náà ni Jóṣúà àti gbogbo Ísírẹ́lì tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Lákíṣì lọ sí Égílónì; wọ́n sì dótì í, wọ́n sì kọ lù ú.

35. Wọ́n gbà á ní ọjọ́ náà, wọ́n sì fi ojú idà kọlù ú, wọ́n sì run gbogbo ènìyàn ibẹ̀ pátapáta, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe sí Lákísì.

36. Nígbà náà ni Jóṣúà àti gbogbo Ísírẹ́lì sí láti Égílónì, lọ sí Hébúrónì, wọ́n sì kọlù ú.

37. Wọ́n gba ìlú náà, wọ́n sìti idà bọ̀ ọ́, pẹ̀lú ọba rẹ̀, gbogbo ìletò wọn àti gbogbo ènìyàn ibẹ̀. Wọn kò dá ẹnìkan sí. Gẹ́gẹ́ bí ti Égílónì, wọ́n run un pátapáta àti gbogbo ènìyàn inú rẹ̀.

38. Nígbà náà ni Jóṣúà àti gbogbo Ísírẹ́lì tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ yí padà, wọ́n sì kọlu Débírì.

39. Wọ́n gba ìlú náà, ọba rẹ̀ àti gbogbo ìlú wọn, wọ́n sì fi idà pa wọ́n. Gbogbo ènìyàn inú rẹ̀ ni wọ́n parun pátapáta. Wọn kò sì dá ẹnìkankan sí. Wọ́n ṣe sí Débírì àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí wọn ti ṣe sí Líbínà àti ọba rẹ̀ àti sí Hébúrónì.

Ka pipe ipin Jóṣúà 10