Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 10:28-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

28. Ní ọjọ́ náà Jóṣúà gba Mákédà. Ó sì fi ojú idà kọlu ìlú náà àti ọba rẹ̀, ó sì run gbogbo wọn pátapáta, kò fi ẹnìkan sílẹ̀. Ó sì ṣe sí ọba Mákédà gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe sí ọba Jẹ́ríkò.

29. Nígbà náà ní Jóṣúà àti gbogbo Ísírẹ́lì tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Mákédà lọ sí Líbínà wọ́n sì kọlù ú.

30. Olúwa sì fi ìlú náà àti ọba rẹ̀ lé Ísírẹ́lì lọ́wọ́. Ìlú náà àti gbogbo àwọn ènìyàn ibẹ̀ ni Jóṣúà fi idà pa. Kò fi ẹnìkan sílẹ̀ ní ibẹ̀: Ó sì ṣe sí ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí ọba Jẹ́ríkò.

31. Nígbà náà ni Jóṣúà àti gbogbo ará Ísírẹ́lì, tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Líbínà lọ sí Lákíṣì; ó sì dótì í, ó sì kọlù ú.

32. Olúwa sì fi Lákísì lé Ísírẹ́lì lọ́wọ́, Jóṣúà sì gbà á ní ọjọ́ kéjì. Ìlú náà àti gbogbo ènìyàn ibẹ̀ ní ó fi idà pá gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Líbínà.

33. Ní àkókò yìí, Hórámì ọba Gésérì gòkè láti ran Lákíṣì lọ́wọ́, ṣùgbọ́n Jóṣúà ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ ogun rẹ̀ títí ti kò fi ku ẹnìkan sílẹ̀.

34. Nígbà náà ni Jóṣúà àti gbogbo Ísírẹ́lì tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Lákíṣì lọ sí Égílónì; wọ́n sì dótì í, wọ́n sì kọ lù ú.

35. Wọ́n gbà á ní ọjọ́ náà, wọ́n sì fi ojú idà kọlù ú, wọ́n sì run gbogbo ènìyàn ibẹ̀ pátapáta, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe sí Lákísì.

36. Nígbà náà ni Jóṣúà àti gbogbo Ísírẹ́lì sí láti Égílónì, lọ sí Hébúrónì, wọ́n sì kọlù ú.

Ka pipe ipin Jóṣúà 10