Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 1:4-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Àwọn ọmọ rẹ̀ a sì máa lọ í jẹun àsè nínú ilé ara wọn, olúkúlùkù ní ọjọ́ rẹ̀; wọn a sì máa ránṣẹ́ pé arábìnrin wọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta láti jẹun àti láti pẹ̀lú wọn.

5. Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ àṣè wọn pé yíká, ni Jóòbù ránṣẹ́ lọ í yà wọ́n sí mímọ́, ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì rú ẹbọ sísun níwọ̀n iye gbogbo wọn; nítorí tí Jóòbù wí pé: bóyá àwọn ọmọ mi ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣọpẹ́ fún Ọlọ́run lọkàn wọn. Bẹ́ẹ̀ ní Jóòbù máa ń ṣe nígbà gbogbo.

6. Ǹjẹ́ ó di ọjọ́ kan, nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá í pé níwájú Olúwa, Sàtánì sì wá pẹ̀lú wọn.

7. Olúwa sì bi Sàtanì wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?”Nígbà náà ní Sàtanì dá Olúwa lóhùn wí pé, “Ní ìlọ-siwá-sẹ́yìn lórí ilẹ ayé, àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”

8. Olúwa sì sọ fún Sàtanì pé ìwọ ha kíyèsí Jóòbù ìránṣẹ́ mi, pé kò sí èkejì rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí í ṣe olóòótọ́, tí ó sì dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ti ó sì kóríra ìwà búburú.

9. Nígbà náà ni sátanì dá Olúwa lóhùn wí pé, “Jóòbù ha bẹ̀rù Olúwa ní asán bí?

10. Ìwọ kò ha ti ṣọgbà yìí ká, àti yí ilé rẹ̀ àti yí ohun tí ó ní ká, ní ìhà gbogbo? Ìwọ bùṣí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì ń pọ si ní ilẹ̀.

11. Ǹjẹ́, nawọ́ rẹ nísinsin yìí, kí ó sì fi tọ́ ohun gbogbo tí ó ni; bí kì yóò sì bọ́hùn ni ojú rẹ”

12. Olúwa sì dá Sàtanì lóhùn wí pé, “Kíyèsí i, ohun gbogbo tí ó ní ń bẹ ní ìkáwọ́ rẹ, kìkì òun tìkára rẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ rẹ kàn.”Bẹ́ẹ̀ ni Sàtanì jáde lọ kúrò níwájú Olúwa.

13. Ó sì di ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, tí wọ́n mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n wọn ọkùnrin:

Ka pipe ipin Jóòbù 1