Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 1:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọkùnrin kan wà ní ilẹ̀ Húsì, orúkọ ẹni tí í jẹ́ Jóòbù; ọkùnrin náà sì ṣe olóòótọ́, ó dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó kórìíra ìwà búburú,

2. A sì bi ọmọkùnrin méje àti ọmọbìnrin mẹ́ta fún un.

3. Ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàarin (7000) àgùntàn, àti ẹgbẹ̀ẹ́dógún (3000) ìbákasíẹ, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (500) àjàgà ọdámàlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (500) abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì pọ̀; bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin yìí sì pọ̀ jù gbogbo àwọn ará ìlà òòrun lọ.

4. Àwọn ọmọ rẹ̀ a sì máa lọ í jẹun àsè nínú ilé ara wọn, olúkúlùkù ní ọjọ́ rẹ̀; wọn a sì máa ránṣẹ́ pé arábìnrin wọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta láti jẹun àti láti pẹ̀lú wọn.

5. Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ àṣè wọn pé yíká, ni Jóòbù ránṣẹ́ lọ í yà wọ́n sí mímọ́, ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì rú ẹbọ sísun níwọ̀n iye gbogbo wọn; nítorí tí Jóòbù wí pé: bóyá àwọn ọmọ mi ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣọpẹ́ fún Ọlọ́run lọkàn wọn. Bẹ́ẹ̀ ní Jóòbù máa ń ṣe nígbà gbogbo.

6. Ǹjẹ́ ó di ọjọ́ kan, nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá í pé níwájú Olúwa, Sàtánì sì wá pẹ̀lú wọn.

7. Olúwa sì bi Sàtanì wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?”Nígbà náà ní Sàtanì dá Olúwa lóhùn wí pé, “Ní ìlọ-siwá-sẹ́yìn lórí ilẹ ayé, àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”

8. Olúwa sì sọ fún Sàtanì pé ìwọ ha kíyèsí Jóòbù ìránṣẹ́ mi, pé kò sí èkejì rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí í ṣe olóòótọ́, tí ó sì dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ti ó sì kóríra ìwà búburú.

Ka pipe ipin Jóòbù 1