Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóẹ́lì 2:6-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Ní ojú wọn, àwọn ènìyàn yóò jẹ ìrora púpọ̀:gbogbo ojú ní yóò ṣú dudu.

7. Wọn yóò sáré bi àwọn alágbára;wọn yóò gùn odi bí ọkùnrin ológun;olúkúlúkù wọn yóò sì rìn lọ ní ọ̀nà rẹ̀,wọn kì yóò sì yà kúrò ni ọ̀nà wọn.

8. Bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò to ẹnìkejì rẹ̀;olúkúlukù wọn yóò rìn ní ọ̀nà rẹ̀:nígbà tí wọn bá sì ṣubú lù ìdàwọn kì yóò gbọgbẹ́.

9. Wọn yóò sáré síwá ṣẹ́yìn ní ìlú;wọn yóò súré lórí odi,wọn yóò gùn orí ilé;wọn yóò gbà ojú fèrèsé wọ̀ inú ilé bí olè.

10. Ayé yóò mì níwájú wọn;àwọn ọ̀run yóò wárìrì;òòrùn àti òṣùpá yóò ṣókùnkùn,àwọn ìràwọ̀ yóò sì fà ìmọ́lẹ̀ wọn ṣẹ́yìn.

11. Olúwa yóò sì bú rámu ramùjáde níwájú ogun rẹ̀:nítorí ibùdó rẹ̀ tóbi gidigidi;nítorí alágbára ní òun, tí n mú ọ̀rọ rẹ̀ ṣẹ;nítorí ọjọ́ Olúwa tóbi ó sì ní ẹ̀rù gidigidi;ara ta ni ó lè gbà á?

12. “Njẹ́ nítorí náà nísínsin yìí,” ni Olúwa wí,“Ẹ fi gbogbo ọkàn yín yípadà sí mi,àti pẹ̀lú ààwẹ̀, àti pẹ̀lú ẹkún, àti pẹ̀lú ọ̀fọ̀.”

13. Ẹ sì fa ọkàn yín ya,kì í sì í ṣe aṣọ yín,ẹ sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run yín,nítorí tí o pọ̀ ní oore ọ̀fẹ́,ó sì kún fun àánú, ó lọ́ra láti bínú,ó sì ṣeun púpọ̀, ó sì ronúpìwàdà láti ṣe búburú.

Ka pipe ipin Jóẹ́lì 2