Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóẹ́lì 1:14-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Ẹ yà ààwẹ̀ kan sí mímọ́,ẹ pe àjọ kan tí o ní ìrònú,ẹ pe àwọn àgbà,àti gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náàjọ sí ilé Olúwa Ọlọ́run yín,kí ẹ sí képe Olúwa

15. A! Fún ọjọ́ náà,nítorí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀,yóò de bí ìparun láti ọwọ́ Olódùmare.

16. A kò ha ké oúnjẹ kúrò níwájúojú wá yìí,ayọ̀ àti inú dídùn kúrò nínú iléỌlọ́run wá?

17. Irúgbìn bàjẹ́ nínú ebè wọn,a sọ àká di ahoro, a wó àká palẹ̀;nítorí tí a mú ọkà rọ.

18. Àwọn ẹranko tí ń kerora tó!Àwọn agbo ẹran dààmú,nítorí tí wọ́n kò ni pápá oko;nítòótọ́, àwọn agbo àgùntàn jìyà.

19. Olúwa, sí ọ ni èmi o ké pè,nítorí iná tí run pápa oko tútú ihà,ọwọ́ iná sí ti jó gbogbo igi igbó.

20. Àwọn ẹranko igbó gbé ojú sókè sí ọ pẹ̀lú:nítorí tí àwọn iṣàn omi gbẹ,iná sí ti jó àwọn pápá oko ihà run.

Ka pipe ipin Jóẹ́lì 1