Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 51:41-51 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

41. “Bí Sésákì yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé.Irú ìpàyà wo ni yóò báBábílónì láàrin àwọn orílẹ̀ èdè!

42. Òkun yóò ru borí Bábílónì,gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Bábílónì.

43. Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro,ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ tí ènìyànkò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.

44. Èmi yóò fi ìyà jẹ Bélì tiBábílónì àti pé èmi yóòjẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì.Orílẹ̀ èdè kò ní i jẹ́ ìṣàn fún-un mọ́.Odi Bábílónì yóò sì wó.

45. “Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ẹ̀yin ènìyàn mi!Sá àṣálà fún ẹ̀mi rẹ!Sá fún ìbínú ńlá Ọlọ́run.

46. Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrútàbí kí o bẹ̀rù nígbà tía bá gbọ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa;àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí,òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipání ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.

47. Nítorí ìgbà náà yóò wádandan nígbà tí èmiyóò fi ìyà jẹ àwọnòrìṣà Bábílónì, gbogbo ilẹ rẹ̀ ni a ó dójú tìgbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárin rẹ̀.

48. Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn,yóò sì kọrin lórí Bábílónì:nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,”ni Olúwa wí.

49. “Gẹ́gẹ́ bí Bábílónì ti mú kí àwọn olùpa Ísírẹ́lì ṣubúbẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ní àwọn olùpa gbogbo ilẹ̀ ayé yóò ṣubú.

50. Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró:Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè,ẹ sì jẹ́ kí Jérúsálẹ́mù wá sí ọkàn yín.”

51. “Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn:ìtìjú ti bò wá lójúnítorí àwọn àlejò wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”

Ka pipe ipin Jeremáyà 51