Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 36:21-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Ọba sì rán Jéhúdù láti lọ mú ìwé kíká náà wá láti inú iyàrá Elisámà akọ̀wé. Ó sì ka ìwé náà ní etí Ọba àti ní etí gbogbo àwọn ìjòyè tí ó dúró ti Ọba.

22. Ó sì jẹ́ ìgbà òtútù nínú oṣù kẹsàn-án, Ọba sì jókòó ní ẹ̀bá iná àrò, iná náà sì ń jó ní iwájú rẹ̀.

23. Nígbà tí Jéhúdù ka ojú ìwé mẹ́ta sí mẹ́rin nínú ìwé náà, Ọba fi ọ̀bẹ gé ìwé, ó sì sọ sínú iná tí ó wà nínú ìdáná, títí tí gbogbo ìwé náà fi jóná tán.

24. Síbẹ̀, Ọba àti gbogbo àwọn ẹmẹ̀wà rẹ̀ tí wọ́n gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí kò bẹ̀rù; wọn kò sì fa aṣọ wọn yá.

25. Elinátanì, Déláyà àti Jemaríà sì bẹ Ọba kí ó má ṣe fi ìwé náà jóná, ṣùgbọ́n Ọba kọ̀ láti gbọ́ ti wọn.

26. Dípò èyí Ọba pàṣẹ fún Jeremélì ọmọ Hamelékì, Seráyà ọmọ Ásíráélì àti Selemáyà ọmọ Ábídélì láti mú Bárúkì akọ̀wé àti Jeremáyà wòlíì ṣùgbọ́n Ọlọ́run fi wọ́n pamọ́.

27. Lẹ́yìn tí Ọba fi ìwé kíkà náà tí ọ̀rọ̀ tí Bárúkì kọ láti ẹnu Jeremáyà jóná tán, ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sì tọ Jeremáyà wá:

Ka pipe ipin Jeremáyà 36