Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 34:19-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Àwọn ìjòyè Júdà àti àwọn ti Jérúsálẹ́mù, àwọn aláṣẹ àti àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó kọjá láàrin àwọn ìpín méjèèjì náà.

20. Èmi ó fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn ọ̀ta wọn, àti lé àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́. Òkú wọn yóò jẹ́ oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún àwọn ẹranko ìgbẹ́.

21. “Sédékáyà Ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀ ní Júdà ni èmí yóò fi lé àwọn ọ̀ta wọn lọ́wọ́, àti àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn àti lé ọwọ́ ogun Bábílónì tí ó ti lọ kúrò lọ́dọ̀ yín.

22. Wò ó èmi ó pàṣẹ ni Olúwa wí, èmi ó sì mú wọn padà sí ìlú yìí, wọn ó sì baà jà, wọn ó sì kóo, wọn ó fi iná jóo. Èmi ó sì sọ ìlú Júdà dí ahoro.”

Ka pipe ipin Jeremáyà 34