Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 31:13-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Àwọn wúndíá yóò jó, wọn ó sì kún fún ayọ̀,bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọkùnrin àti obìnrin.Èmi yóò sọ ọ̀fọ̀ wọn di ayọ̀,dípò ìkorò èmi yóò tù wọ́n nínú.Èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀.

14. Èmi ó tẹ́ àwọn àlùfáà lọ́rùn pẹ̀lú ọ̀pọ̀;àwọn ènìyàn mi yóò sì kún fún oore mi,”ni Olúwa wí.

15. Èyí ni ohun tí Olúwa wí:“A gbọ́ ohùn kan ní Rámàtí ń sọ̀fọ̀ pẹ̀lú ẹkún kíkorò.Rákélì ń sọkún fún àwọn ọmọ rẹ̀;kò gbà kí wọ́n tu òun nínú,nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”

16. Báyìí ni Olúwa wí:“Dá ohùn rẹ dúró nínú ẹkúnàti ojú rẹ nínú omijé;nítorí a ó fi èrè sí isẹ́ rẹ,”ni Olúwa wí.“Wọn ó sì padà wá láti ilẹ̀ ọ̀tá.

17. Nítorí ìrètí wà fún ọjọ́ iwájú rẹ,”ni Olúwa wí.“Àwọn ọmọ rẹ yóò padà wá sí ilẹ̀ wọn.

18. “Nítòótọ́, èmi ti gbọ́ ìpohùnréré Éfúráímù wí pé,‘Ìwọ ti bá mi wí gẹ́gẹ́ bí ọmọ màlúù tí a kò kọ́èmi sì ti gbọ́ ìbáwí.Ràmípadà, Èmi yóò sì yípadà,nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run mi.

19. Lẹ́yìn tí mo ti ronúpìwàdà,èmi jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi,lẹ́yìn tí mo ti mọ̀,èmi lu àyà mi.Ojú tì mí, mo sì dààmú;nítorí èmi gba èrè ẹ̀gàn ìgbà èwe mi.’

20. Éfúráímù kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradáratí inú mi dùn sí bí?Bí èmi ti ń sọ̀rọ̀ sí i tó,síbẹ̀, èmi rántí rẹ̀.Nítorí náà, ọkàn mi ṣe ohun kan fún un,èmi káàánú gidigidi fún un,”ni Olúwa wí.

21. “Gbé àmì ojú ọ̀nà dìde,ṣe atọ́nà àmì,kíyèsí pópónà rélùwéèojú ọ̀nà tí ó ń gbà.Yípadà ìwọ wúndíá Ísírẹ́lì,padà sí àwọn ìlú rẹ.

22. Ìwọ yóò ti sìnà pẹ́ tó,ìwọ aláìsòótọ́ ọmọbìnrin; Olúwa yóò dá ohun tuntun lórí ilẹ̀,ọmọbìnrin yóò yí ọkùnrin kan ká.”

23. Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ ogun Ísírẹ́lì wí: “Nígbà tí èmi bá kó wọn dé láti ìgbèkùn; àwọn ènìyàn tí ó wà ní ilẹ̀ Júdà àti ní àwọn ìlú rẹ̀ yóò tún lo àwọn ọ̀rọ̀ yìí lẹ́ẹ̀kan síi; wí pé, ‘Olúwa bùkún fún ọ, ìwọ tí ń gbé nínú òdodo, ìwọ òkè ìwà mímọ́.’

24. Àwọn ènìyàn yóò gbé papọ̀ ní Júdà àti ní gbogbo àwọn ìlú rẹ̀; bákan náà ni àgbẹ̀ àti àwọn tí ń tẹ̀lé agbo ẹran wọn ká.

25. Èmi yóò sọ aláàárẹ̀ di ọ̀tun, èmi yóò sì tẹ́ gbogbo ọkàn tí ń káànú lọ́rùn.”

26. Lórí èyí ni mo jí, mo sì wò yíká, oorun mi sì dùn mọ́ mi.

27. “Wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí èmi yóò gbin ilé Ísírẹ́lì àti ilé Júdà pẹ̀lú irúgbìn ọmọ ènìyàn àti ẹranko.

Ka pipe ipin Jeremáyà 31