Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 28:5-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Wòlíì Jeremáyà fún wòlíì Hananáyà lésì ní iwájú ọmọ àlùfáà àti àwọn ènìyàn tí wọ́n dúró ní ilé Olúwa.

6. Ó sọ wí pé, “Àmín! Kí Olúwa ó ṣe bẹ́ẹ̀! Kí Olúwa ó mú àwíṣẹ àsọtẹ́lẹ̀ nípa ohun èlò ilé Olúwa àti gbogbo àwọn aṣàtìpó padà sí ilẹ̀ Bábílónì.

7. Nísinsìnyìí, tẹ́tí sí àwọn ohun tí mo sọ fún gbígbọ́ àti fún gbígbọ́ gbogbo ènìyàn.

8. Ní ìbẹ̀rẹ̀ àwọn wòlíì tí ó ṣáájú rẹ àti èmi ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ogun, ibi àti àjàkálẹ̀ sí ọ̀pọ̀ orílẹ̀ èdè.

9. Ṣùgbọ́n, àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ àlàáfíà ni a mọ̀ gẹ́gẹ́ bí wòlíì olótítọ́ tí Olúwa rán, tí àṣọtẹ́lẹ̀ rẹ bá wá sí ìmúṣẹ.”

10. Wòlíì Hananáyà gbé àjàgà ọrùn wòlíì Jeremáyà kúrò, ó sì fọ́ ọ.

Ka pipe ipin Jeremáyà 28