Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 23:11-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. “Wòlíì àti àlùfáà kò gbé ìgbé ayé ìwàbí Ọlọ́run;kódà nínú Tẹ́ḿpìlì mi ni mo rí ìwà búburú wọn,”ni Olúwa wí.

12. “Nítorí náà, ọ̀nà wọn yóò di yíyọ́,a ó lé wọn jáde sínú òkùnkùn;níbẹ̀ ni wọn yóò ṣubú.Èmi yóò mú ìdààmú wá sórí wọn,ní ọdún tí a jẹ wọ́n níyà,”ni Olúwa wí.

13. “Láàrin àwọn wòlíì Saáríà,Èmi rí ohun tí ń lé ni sá:Wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ Báálìwọ́n sì mú Ísírẹ́lì ènìyàn mi sìnà.

14. Àti láàrin àwọn wòlíì Jérúsálẹ́mù,èmi ti rí ohun búburú:Wọ́n ṣe panṣágà, wọ́n sì ń ṣèké.Wọ́n fún àwọn olùṣe búburú ní agbára,tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí ó yípadà kúrò nínú ìwà búburú rẹ̀.Gbogbo wọn dàbí Sódómù níwájú mi,àti àwọn ènìyàn olùgbé rẹ̀ bí Gòmórà.”

15. Nítorí náà, báyìí ni OlúwaỌlọ́run alágbára wí ní ti àwọn wòlíì:“Èmi yóò mú wọn jẹ oúnjẹ kíkorò,wọn yóò mu omi májèlénítorí láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì Jérúsálẹ́mùni àìwà-bí-Ọlọ́run ti tàn ká gbogbo ilẹ̀.”

16. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí,“Ẹmá ṣe fi etí sí àṣọtẹ́lẹ̀ tí àwọn wòlíì èké ń sọ fún un yín.Wọ́n ń kún inú ọkàn yín pẹ̀lú ìrètí asán.Wọ́n ń sọ ìran láti ọkàn ara wọn,kì í ṣe láti ẹnu Olúwa.

17. Wọ́n ń sọ fún àwọn tí ó ń gàn mí pé,‘Olúwa ti wí pé: Ẹ ó ní àlàáfíà,’Wọ́n sì wí fún gbogbo àwọn tí ó rìn nípa agídí ọkàn rẹ̀ pé,‘Kò sí ìpalára kan tí yóò ṣẹlẹ̀ sí yín.’

18. Ṣùgbọ́n èwo nínú wọn ni ó dúrónínú ìgbìmọ̀ Olúwa láti rí itàbí gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀?Ta ni ó gbọ́ tí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ náà?

19. Wò ó, afẹ́fẹ́ Olúwa yóò tú jádepẹ̀lú ìbínú àfẹ́yíká ìjì yóò fẹ́ síorí àwọn olùṣe búburú.

20. Ìbínú Olúwa kì yóò yẹ̀títí tí yóò sì fi mú èrò rẹ̀ ṣẹ,ní àìpẹ́ ọjọ́, yóò yé e yín yékéyéké.

21. Èmi kò rán àwọn wòlíì wọ̀nyísíbẹ̀ wọ́n lọ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọn.Èmi kò tilẹ̀ bá wọn sọ̀rọ̀,síbẹ̀ wọ́n sọ àṣọtẹ́lẹ̀,

22. Ṣùgbọ́n ìbáṣepọ̀ wọn dúró nínú ìgbìmọ̀ mi,wọn ì bá ti kéde ọ̀rọ̀ mi fún àwọn ènìyàn mi.Wọn ì bá ti wàásù ọ̀rọ̀ mi sí àwọn ènìyànwọn ìbá ti yípadà kúrò nínú ọ̀nààti ìṣe búburú wọn.

Ka pipe ipin Jeremáyà 23