Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 10:1-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ fún yín ẹ̀yin ilé Ísírẹ́lì.

2. Èyí ni ohun tí Olúwa wí:“Má se tọ ọ̀nà àwọn orílẹ̀ èdètàbí kí ẹ jẹ́ kí àmù òfuurufú dààmúyín, nítorí pé wọ́n ń dààmú orílẹ̀ èdè.

3. Nítorí pé asán ni asà àwọn ènìyàn,wọ́n gé igi láti inú igbó, oníṣẹ́-ọnàsì gbẹ́ ẹ pẹ̀lú àáké rẹ̀.

4. Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe élọ́sọ̀ọ́. Wọ́n fi òòlù kàn án àtièṣo kí ó má ba à ṣubú.

5. Wọ́n nàró bí igi ọ̀pẹ, òrìṣà wọnkò le è ṣọ̀rọ̀. Wọ́n gbọdọ̀ máa gbéwọn nítorí pé wọn kò lè rìn. Má ṣebẹ̀rù wọn; wọn kò le è ṣe ibi kankanbẹ́ẹ̀ ni wọn kò si lè ṣe rere kan.”

6. Kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ Olúwa;o tóbi orúkọ rẹ sì tóbi lágbára.

7. Ta ni kò yẹ kí ó bẹ̀rù rẹ Ọba àwọnorílẹ̀ èdè? Nítorí tìrẹ ni, láàrin àwọnọlọ́gbọ́n ènìyàn ní orílẹ̀ èdè àtigbogbo ìjọba wọn, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ.

8. Gbogbo wọn jẹ́ aláìlóye àti òpè, wọ́nń kọ́ ẹ̀kọ́ àwọn ère igi tí kò ní láárí

9. Sílífà tí a ti kàn ni a mú wá látiTásísì, àti wúrà láti Lépásì; èyí tíàwọn onísọ́nà àti alágbẹ̀dẹ ṣe tí wọ́nkùn ní àwọ̀ aró àti eléṣé àlùkò,èyí jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n oníṣẹ́.

10. Ṣùgbọ́n Olúwa ni Ọlọ́run tòótọ́,òun ni Ọlọ́run alààyè, Ọba ayérayé.Nígbà tí ó bá bínú, ayé yóò wárìrì;orílẹ̀ èdè kò lè fi ara da ìbínú rẹ̀.

11. “Sọ èyí fún wọn: ‘Àwọn ọlọ́run kékèèké tí kò dá ọ̀run àti ayé ni yóò ṣègbé láti ayé àti ní abẹ́ ọ̀run.’ ”

12. Ọlọ́run dá ayé pẹ̀lú agbára rẹ̀,ó dá àgbáyé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀,ó mú kí ọ̀run kí ó fẹ̀ tóbi síta nípa òye rẹ̀.

13. Nígbà tí ó bá sán àrá, àwọn omilọ́run a sì pariwo, ó mú kí ìkuùkù rusókè láti òpin ayé: ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò,ó sì ń mú afẹ́fẹ́ wá láti ilé ìṣúra rẹ̀.

14. Gbogbo ènìyàn jẹ́ aláìlóye àti aláìnímọ̀,ojú sì ti gbogbo alágbára pẹ̀lú ère rẹ̀,èrú ni ère rẹ̀, kò sì sí ẹ̀mí nínú wọn.

Ka pipe ipin Jeremáyà 10