Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 45:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “ ‘Nígbà ti ẹ̀yin bá pín ilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ogún, ẹ gbọdọ̀ gbé ìpín ilẹ̀ kan kalẹ̀ fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí agbègbè mímọ́, ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n ìgbọ̀nwọ́ ni gígùn àti ogún ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́ ni fífẹ̀; gbogbo agbègbè náà ni yóò jẹ́ mímọ́.

2. Lára èyí, apákan ti ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ kọ̀ọ̀kan tí o jẹ́ ẹ̀ẹ́dégbẹ̀ta ìgbọ̀nwọ́ ní ó gbọdọ̀ wà fún ibi ìyàsímúmọ́ fún Ọlọ́run, pẹ̀lú ibẹ̀ tí ó jẹ́ àádọ́ta ìgbọ̀nwọ́ fún ilẹ̀ tí ó yí ibi mímọ́ náà ká. Ilẹ̀ tí ó yí i ká yìí yóò wà bẹ́ẹ̀ láì lò ó.

3. Ní agbègbè ibi mímọ́, wọn ya ibi kan sọ́tọ̀ kí ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n ìgbọ̀nwọ́ gígùn àti ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní fífẹ̀. Ní inú rẹ ni ilẹ̀ ti a yà sọ́tọ̀ fún Olúwa yóò wà, ìyẹn ibi mímọ́ jùlọ.

4. Yóò jẹ́ ibi mímọ́ lára ilẹ̀ náà fún àwọn àlùfáà, tí ó ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ibi mímọ́ àti àwọn tí ó súnmọ́ àlùfáà ní iwájú Olúwa. Ibẹ̀ yóò jẹ ibi tí yóò wà fún ilé gbígbé wọn, bákan náà ni yóò jẹ́ ibi mímọ́ fún ilé Olúwa.

5. Agbègbè kan tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn àti ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá ní fífẹ̀ yóò jẹ́ ti àwọn ará Léfì, tí ó ń ṣiṣẹ ìránṣẹ́ nínú tẹ́ḿpìlì, gẹ́gẹ́ bi ìní wọn fún ìlú wọn láti máa gbé ibẹ̀.

6. “ ‘Ìwọ yóò fi ìlú náà ti agbègbè rẹ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ìgbọ̀nwọ́ ni fífẹ̀ àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn, papọ̀ mọ́ ibi mímọ́ fún àwọn ilé Ísírẹ́lì gẹ́gẹ́ bí ìní: yóò jẹ́ ti gbogbo ilé Ísírẹ́lì.

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 45