Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 44:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Lẹ́yìn náà ni ọkùnrin náà mú mi padà lọ sí ibi mímọ́, èyí tí ó kọjú sí ìhà ìlà oòrùn, ó sì wà ní títì.

2. Olúwa sọ fún mi, “Ẹnu ọ̀nà yìí ni kí ó wà ní títì. A kò gbọdọ̀ sí i sílẹ̀; kò sí ẹni tí o gbọdọ̀ gba ibẹ̀ wọlé. Ó gbọdọ̀ wà ní títì nítorí pé Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì tí gbà ibẹ̀ wọlé.

3. Ọmọ aládé fúnra rẹ̀ ní o lè jókòó ní ẹnu ọ̀nà náà kí o sì jẹun níwájú Olúwa. Ó gbọdọ̀ gba ọ̀nà ìlóro ẹnu ọ̀nà wọlé kí ó sì gba ibẹ̀ jáde.”

4. Lẹ́yìn náà, ọkùnrin náà mú mi gba ẹnu ọ̀nà àríwá lọ sí iwájú ilé Ọlọ́run. Mo wò ó mo sì rí ògo Olúwa tí ó kún inú ilé Olúwa, mo sì dojúkọ ilẹ.

5. Olúwa sì sọ fún mì pé, “Ọmọ ènìyàn, wò dáadáa, fetí sílẹ̀ dáadáa kí o sì fiyèsí ohun gbogbo tí mo sọ fún ọ nípa ofin lórí ilé Olúwa náà. Fiyèsí ẹnu ọ̀nà ilé Ọlọ́run náà àti gbogbo àbájáde ibi mímọ́.

6. Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé Ísírẹ́lì pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Ọba wí: Ìwà ìríra rẹ tí tó gẹ́ẹ́, ìwọ ilé Ísírẹ́lì!

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 44