Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 40:4-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ọkùnrin náà sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, wò pẹ̀lú ojú rẹ kí o sì gbọ́ pẹ̀lú etí rẹ, kí ó sì farabalẹ̀ sì gbogbo ohun tí mo máa fi hàn ọ, nítorí ìdí nìyí tí a fi mú ọ wá síhìn-ín. Sọ gbogbo ohun tí ó bá rí fún ilé Ísírẹ́lì.”

5. Mo rí ògiri tí ó yí agbègbè ibi mímọ̀ po. Gígùn ọ̀pá ìwọnlẹ̀ tí ó wà ní ọwọ́ ọkùnrin náà sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́fà, ọkọ̀ọ̀kan sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan àti ilásì mẹ́rin ẹsẹ̀ bàtà. Ó wọn ògiri náà; ó jẹ́ ìwọ̀nyí ọ̀pá náà ni níní ipọn, ó sì jẹ́ ọ̀pá kan ní gíga.

6. Lẹ́yìn náà ni ó wá lọ sí ẹnu ọ̀nà òde tí ó kọjú sí ìlà òòrùn. Ó gun àtẹ̀gùn rẹ̀, o sì wọn ìloro ẹnu ọ̀nà ilé; ó jẹ́ ọ̀pa kan ní jíjìn.

7. Yàrá kéékèèkéé sì jẹ ọ̀pá kan ni gígùn àti ọpá kan ní ibú, ìgbéró ògiri àárin yàrá kéékèèkéé náà jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún ni nínípọn. Ìloro ẹnu ọ̀nà náà tí ó kángun sí àtẹ̀wọ́ ẹnu ọ̀nà náà tó kọjú sì tẹ́ḿpìlì jẹ́ ọ̀pá kan ní jíjìn.

8. Lẹ́yìn náà, ó wọn àtẹ̀wọ́ ẹnu ọ̀nà:

9. Ó jẹ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́jọ ní jíjìn àtẹ́rígbà rẹ̀ sì jẹ ìgbọ̀nwọ́ méjì ní nínípọ̀n. Àtẹ̀wọ̀ ẹnu ọ̀nà kọjú sí tẹ́ḿpìlì.

10. Ní ẹnu ọ̀nà ìlà òòrùn ni àwọn yàrá kéékèèkéé mẹ́ta wà ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan: mẹ́tẹ̀ẹ̀ta kọ̀ jú sí ara wọn, ojú ìgbéró ògiri ni ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan jẹ́ bákan náà ní wíwọ̀n.

11. Lẹ́yìn náà ó wọn ìbú à bá wọ ẹnu ọ̀nà náà; ó jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wà, gígùn rẹ̀ sì jẹ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́tàlá.

12. Ní iwájú ọ̀kọ̀ọ̀kan yàrá kéékèèkéé kọ̀ọ̀kan ní ògiri tí gíga rẹ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan wà, ẹ̀gbẹ́ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin àwọn yàrá kéékèèkéé sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́fà.

13. Lẹ́yìn náà, ó wọn ẹnu ọ̀nà láti òkè ẹ̀yìn ògiri yàrá kéékèèkéé kan títí dé òkè àdojúkọ ọ̀kan; jínjìn sí ara wọn jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ́dọ́gbọ̀n láti odi kan tí ó sí sílẹ̀ sí àdojúkọ ọ̀kan.

14. Ó wọ̀n ọ́n lọ sí àwọn ojú àwọn ìgbéró ògiri gbogbo rẹ̀ yí inú òjú ọ̀nà ó jẹ́ ọgọ́ta ìgbọ̀nwọ́. Ìwọ̀n náà tó àtẹ̀wọ́ ẹnu ọ̀nà tí ó dojúkọ àgbàlá.

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 40