Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 40:34-40 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

34. Àtẹ̀wọ̀ ẹnu ọ̀nà rẹ̀ dojúkọ àgbàlá tí ìta; àwọn igi ọ̀pẹ ṣe ọ̀sọ́ sí àtẹ́rígbà ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì, àtẹ̀gùn mẹ́jọ sì lọ sókè rẹ̀.

35. Gẹ́gẹ́ bí àwọn yàrá kéékèèkéé rẹ̀ ṣe rí. Àwọn ìgbéró ògiri rẹ̀ àti àtẹ̀wọ̀ ẹnu ọ̀nà, ó sì ní àwọn ihò yí i po. O jẹ́ àádọ́ta ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn àti ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ̀dọgbọ̀n ní fífẹ̀.

36. Àwọn yàrá ẹ̀sọ́ rẹ̀ àwọn òpó rẹ̀ àti ìloro rẹ̀, àti fèrèsé rẹ̀ yíká: gígùn rẹ̀ àádọ́ta ìgbọ̀nwọ́, àti ìbú rẹ̀ ìgbọ̀nwọ́ mẹẹdọ́gbọ̀n.

37. Àtẹ̀wọ̀ ẹnu ọ̀nà rẹ̀ dojúkọ àgbàlá ìta; àwọn igi ọ̀pẹ ṣe ọ̀sọ́ sí àwọn àtẹ́rígbà rẹ̀ ni ẹ̀gbẹ́ méjèèjì, àtẹ̀gùn mẹ́jọ ní ó so mọ́ ọn lókè.

38. Yàrá kan pẹ̀lú ilẹ̀kùn wà ní ẹ̀gbẹ́ àtẹ̀wọ̀ ẹnu ọ̀nà ní ọ̀kọ́ọ́kan ẹnu ọ̀nà inú, níbi tí wọn tí ń fọ àwọn ẹbọ sísun.

39. Ní àtẹ̀wọ̀ ẹnu ọ̀nà tí ẹnu ọ̀nà ni tẹ́ḿpìlì méjì wà ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan, lórí èyí tí a ti ń pá ọrẹ ẹbọ sísun, ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹbọ ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀.

40. Ní ẹ̀gbẹ́ ògiri ìta àtẹ̀wọ́ ẹnu ọ̀nà tí ẹnu ọ̀nà, tí ó súnmọ́ àwọn àtẹ̀gùn ní àbáwọlé tí ẹnu ọ̀nà àríwá ni tẹ́ḿpìlì méjì wà, ní ẹ̀gbẹ́ kejì tí àtẹ̀gùn ní tẹ́ḿpìlì méjì wà.

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 40