Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 32:1-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kejìlá, ọdún kejìlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:

2. “Ọmọ ènìyàn, ṣe ìpohùnréré ẹkún nítorí Fáráò Ọba Éjíbítì kí o sì wí fún un:“ ‘Ìwọ dàbí kìnnìún láàárin àwọnorílẹ̀ èdè náà;ìwọ dàbí ohun abanilẹ́rù inú àwọn okun to ń lọkáàkiri inú àwọn odò rẹ,ìwọ fi ẹsẹ rẹ tẹ omiláti mú kí àwọn odò ní ẹrẹ̀.

3. “ ‘Èyí yìí ńi Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:“ ‘Pẹ̀lu ọ̀pọ̀ ìpéjọ ènìyànÈmi yóò da àwọ̀n mi bò ọ́wọn yóò sì fà ọ́ sókè nínú àwọ̀n mi.

4. Èmi yóò jù ọ́ sí orí ilẹ̀èmi yóò sì fà ọ́ sókè sí orí pápá gbangba.Èmi yóò jẹ́ kí gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ṣeàtìpó ní orí rẹ.Gbogbo àwọn ẹranko ayé yóò fiìwọra gbé ara wọn mù lórí rẹ.

5. Èmi yóò tan ẹran ara rẹ ká sóríàwọn òkè gígaìyókù ara rẹ ní wọn yóò fi kúnàwọn àárin àwọn òkè gíga

6. Ẹ̀jẹ̀ rẹ ti ń ṣàn ní èmi yóò sì fi rin ilẹ̀ náàgbogbo ọ̀nà sí orí àwọn òkè gíga,àwọn àlàfo jínjìn ní wọn yóò kún fún ẹran ara rẹ.

7. Nígbà tí mo bá fọ́n ọ jáde, èmi yóò pa ọ̀run déàwọn ìràwọ̀ wọn yóò sì ṣókùnkùn;èmi yóò sì fi ìkùukùu bo oòrùnòṣùpá kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀ rẹ̀

8. Gbogbo ìmọ́lẹ̀ títàn ní ojú ọ̀runni èmi yóò mú ṣókùnkùn lórí rẹ;èmi yóò mú òkùnkùn wá sórí ilẹ rẹ,ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí

9. Èmi yóò da ọkàn ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn rúnígbà tí mo bá mú ìparun rẹ wání àárin àwọn orílẹ̀ èdè tí ìwọkò í tí ì mọ̀.

10. Èmi yóò mú kí ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn dẹ́rù bà ọ́,àwọn Ọba wọn yóò sì wárìrì fúnìbẹ̀rù pẹ̀lú ìpayà nítorí rẹ,nígbà tí mo bá ju idà mi ní iwájú wọnNí ọjọ́ ìṣubú rẹìkọ̀ọ̀kan nínú wọn yóò wárìrìní gbogbo ìgbà fún ẹ̀mí rẹ.

11. “ ‘Nítorí èyí yìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:“ ‘Idà Ọba Bábílónìyóò wá sí orí rẹ,

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 32