Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 30:11-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Òun àti àwọn ológun rẹ̀ẹ́rù àwọn orílẹ̀-èdèní a o mú wá láti pa ilẹ náà run.Wọn yóò fa idà wọn yọ sí Éjíbítìilẹ̀ náà yóò sì kún fún àwọn tí a pa.

12. Èmi yóò mú kí àwọn odò Náílì gbẹÈmi yóò sì ta ilẹ náà fún àwọn ènìyàn búburú:láti ọwọ́ àwọn àjòjì ènìyànÈmi yóò jẹ́ kí ilẹ̀ náà àti gbogbo ohun tí ó wá nínú rẹ ṣòfò.Èmi Olúwa ni ó ti sọ ọ́.

13. “ ‘Báyìí ní Olúwa Ọlọ́run wí:“ ‘Èmi yóò pa àwọn òrìṣà runÈmi yóò sì mú kí òpin dé báère òrìṣà gbígbẹ́ ni Nófìkò ní sí ọmọ aládé mọ́ ní Éjíbítì,Èmi yóò mú kí ìbẹ̀rù gba gbogbo ilẹ̀ náà.

14. Èmi yóò sì mú kí Pátírọ́sì di ahoroèmi yóò fi ina sí Sóánìèmi yóò sì fi ìyà jẹ Tébésì

15. Èmi yóò tú ìbínú mi jáde sórí Pélúsíómùìlú odi Éjíbítìèmi yóò sì ké àkójọpọ̀ Jépésì kúrò

16. Èmi yóò ti iná bọ ÉjíbítìPélúsíómù yóò japoró ní ìroraÈfúùfù yóò jà ní TébésìMémìfísì yóò wà ìpọ́njú ní ìgbà gbogbo

17. Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ní Hẹ́lópónísè àti Búbásítìyóò ti ipa idà subúwọn yóò sì kó àwọn ìlú wọn ní ìgbèkùn

18. Ojú ọjọ́ yóò ṣókùnkùn ní Tápárebìnígbà tí mo bá já àjàgà Éjíbítì kúrò;níbẹ̀ agbára iyì rẹ̀ yóò dópinwọn yóò fi ìkùukùu bò óàwọn abúlé rẹ ní wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.

19. Nítorí náà Èmi yóò mú ki ìjìyà wá sórí Éjíbítì,wọn yóò sì mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.’ ”

20. Ní ọjọ́ keje osù kìn-ín-ní ọdún kọkànlá ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 30