Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 10:15-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. A gbé àwọn kérúbù sókè. Èyí ni àwọn ẹ̀dá alààyè tí mo rí létí odò Kébárì.

16. Bí àwọn kérúbù yìí bá ń lọ àwọn kẹ̀kẹ́ ẹgbẹ́ wọn náà yóò lọ; bẹ́ẹ̀ ni bí àwọn kérúbù bá tú ìyẹ́ wọn ká láti dìde nílẹ̀, àwọn kẹ̀kẹ́ yìí kò ní kúrò lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn.

17. Bí àwọn kérúbù bá dúró díẹ̀ àwọn kẹ̀kẹ́ náà yóò dúró jẹ́ẹ́; bí àwọn kérúbù bá dìde àwọn kẹ̀kẹ́ náà yóò dìde, nítorí pé ẹ̀mí àwọn ẹ̀dá alààyè yìí wà nínú wọn.

18. Ògo Olúwa kúrò níbi ìloro tẹ́ḿpìlì ó sì dúró sórí àwọn kérúbù.

19. Àwọn kérúbù gbé ìyẹ́ wọn sókè, wọ́n sì fò kúrò nílẹ̀ lójú mi, wọ́n sì lọ pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ wọn lẹ́ẹ̀kan náà. Wọ́n dúró níbi ìlẹ̀kùn ẹnu ọ̀nà ìlà-oòrùn ilé Olúwa, ògo Ọlọ́run Ísírẹ́lì sì wà lórí wọn.

20. Àwọn wọ̀nyí ni ẹ̀dá alààyè tí mo rí lábẹ́ Ọlọ́run Ísírẹ́lì létí odò Kébárì, mo sì mọ̀ pé kérúbù ni wọ́n.

21. Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní ojú mẹ́rin àti ìyẹ́ mẹ́rin, lábẹ́ ìyẹ́ wọn ni ohun tó jọ ọwọ́ ènìyàn wà.

22. Àfiwé ojú àti ìrísí wọn rí bákan náà pẹ̀lú àwọn tí mo rí létí odò kébárì. Olúkúlùkù wọn sì ń lọ sí ọ̀kánkán tààrà.

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 10