Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hósíà 9:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Má ṣe yọ̀, ìwọ Ísírẹ́lì;má ṣe hó ìhó ayọ̀ bí àwọn orílẹ̀ èdè yòókù.Nítorí ẹ ti jẹ́ aláìsòótọ́ si lọ́run yín.Ẹ fẹ́ràn láti gbowó iṣẹ́ àgbèrèní gbogbo ilẹ̀ ìpàkà.

2. Àwọn ilé ìpàkà àti ilé ìfun wáìnì kò ní fún àwọn ènìyàn lóúnjẹwáìnì tuntun yóò tàn láìròtẹ́lẹ̀

3. Wọn kò ní ṣẹ́kù sí ilé OlúwaÉfúráímù yóò padà sí ÉjíbítìYóò sì jẹ oúnjẹ àìmọ̀ ní Ásíríà.

4. Wọn kò ní fi ọrẹ ohun mímu fún Olúwa.Bẹ́ẹ̀ ni ìrúbọ wọn kò ní mú, inú rẹ̀ dùn.Ìrú ẹbọ bẹ́ẹ̀ yóò dàbí oúnjẹ àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀.Gbogbo àwọn tó bá sì jẹ ẹ́ yóò di aláìmọ́.Oúnjẹ yìí yóò wà fún wọn fúnra wọnkò ńi wá sí orí tẹ́ḿpìlì Olúwa

Ka pipe ipin Hósíà 9