Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹkún Jeremáyà 2:20-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. “Wòó, Olúwa, kí o sì rò ó:Ta ni ìwọ ti fìyà jẹ bí èyíǸjẹ́ àwọn obìnrin yóò ha jẹ ọmọ wọn,àwọn ọmọ tí wọn ń se ìtọ́jú fún?Ǹjẹ́ kí a pa olórí àlùfáà àti àwọn wòlíìní ibi mímọ́ Olúwa?

21. “Ọmọdé àti àgbà ń sùn papọ̀sínú eruku àwọn òpópó;àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin miti ṣègbé nípa idà.Ìwọ pa wọ́n run ní ọjọ́ ìbínú rẹ;Ìwọ pa wọ́n láìní àánú.

22. “Bí ó ti ṣe ní ọjọ́ àṣè,bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe fi ẹ̀rù sí ẹ̀gbẹ́ mi.Ní ọjọ́ ìbínú Olúwakòsí ẹni tí ó sálà tí ó sì yè;àwọn tí mo ti tọ́jú tí mo sì fẹ́ràn,ni ọ̀ta mi parun.”

Ka pipe ipin Ẹkún Jeremáyà 2