Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹkún Jeremáyà 1:6-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Gbogbo ẹwà ti di ohun ìgbàgbé.Àwọn ọmọ ọba kùnrin dàbí i ìgalàtí kò rí ewé tútù jẹ;nínú àárẹ̀ wọ́n sáréníwájú ẹni tí ó ń lé wọn.

7. Ní ọjọ́ ìpọ́njú àti àrìnká rẹ̀ niJérúsálẹ́mù rántí àwọn ohun ìní dáradára rẹ̀tí ó jẹ́ tirẹ̀ ní ọjọ́ pípẹ́.Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ṣubú sọ́wọ́ àwọn ọ̀tá,kò sì sí olùrànlọ́wọ́ fún un.Àwọn ọ̀tá rẹ̀ wò ówọ́n sì ń fi ìparun rẹ̀ ṣẹlẹ́yà.

8. Jérúsálẹ́mù sì ti dẹ́ṣẹ̀ púpọ̀ó sì ti di aláìmọ́.Àwọn tí ó ń tẹríba fún un sì kẹ́gàn rẹ̀,nítorí wọ́n ti rí ìhòòhò rẹ̀;ó kérora fúnra rẹ̀,ó sì lọ kúrò.

9. Ìdọ̀tí wà ní etí aṣọ rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni kò wo ọjọ́ iwájú rẹ̀,Ìṣubú rẹ̀ ya ni lẹ́nu;olùtùnú kò sì sí fún un.“Wo ìpọ́njú mi, Olúwa,nítorí àwọn ọ̀ta ti borí.”

10. Ọ̀tá ti gbọ́wọ́ légbogbo ìní rẹ;o rí àwọn ìlú abọ̀rìṣàtí wọ́n wọ ibi mímọ́ rẹ—àwọn tí o ti kọ̀ sílẹ̀láti wọ ìpéjọpọ̀ rẹ.

11. Àwọn ènìyàn rẹ̀ ń kérorabí wọ́n ti ń wá oúnjẹ;wọ́n fi ohun ìní wọn se pàsípààrọ̀ oúńjẹláti mú wọn wà láàyè.“Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó,nítorí a kọ̀ mí sílẹ̀.”

12. “Kò ha jẹ́ nǹkankan sí i yín?Gbogbo ẹ̀yin tí ń ré kọjá,Ǹjẹ́ ẹnìkan ń jìyà bí èmi ti ń jìyàtí a fi fún mi, ti Olúwa mú wá fún miní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ̀.

Ka pipe ipin Ẹkún Jeremáyà 1