Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 29:3-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ìwọ yóò sì kó wọn sínú àpẹ̀rẹ̀ kan, ìwọ yóò sì mú wọn wà nínú apẹ̀rẹ̀ náà—papọ̀ pẹ̀lú akọ màlúù àti àgbò méjì náà.

4. Nígbà náà ni ìwò yóò mú Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ wá sí ẹnu ọ̀nà àgọ́ àjọ, ìwọ yóò sì fi omi wẹ̀ wọ́n.

5. Ìwọ yóò sì fi ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọ Árónì, àti aṣọ ìgúnwà éfódì, àti éfódì, àti ìgbàyà, kí ó sì fi onírúurú-ọnà ọ̀já ẹ̀wù èfòdì dìí.

6. Ìwọ yóò sì fí fìlà dé e ní orí, ìwọ yóò sì se adé mímọ́ sára fìlà náà.

7. Nígbà náà ni ìwọ yóò sì mú òrórò ìtasórí, ìwọ yóò sì yà á sí mímọ́ nípa dída òróró sí i ní orí.

8. Ìwọ yóò sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ ìwọ yóò sì fi aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀ wọ́n

9. ìwọ yóò sì fi fìlà dé wọn ni orí. Nígbà náà fi ọ̀já àmùrè di Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀. Iṣẹ́ àlùfáà yóò máa jẹ́ ti wọn ní ìlànà títí ayé. Báyìí ni ìwọ yóò sì ya Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ sí mímọ́.

10. “Ìwọ yóò sì mú akọ màlúù wá ṣíwájú àgọ́ àjọ, Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì fi ọwọ́ lé wọn ní orí.

11. Ìwọ yóò sì pa àwọn akọ màlúù náà níwájú Olúwa ní ẹnu ọ̀nà àgọ́ àjọ.

12. Ìwọ yóò sì mú nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù náà, ìwọ yóò sì fi ìka rẹ tọ́ ọ sára ìwo pẹpẹ náà, kí o sì da gbogbo ẹ̀jẹ̀ tó kù sí ìṣàlẹ̀ pẹpẹ náà.

13. Kí o mú gbogbo ọ̀rá tí ó yí inú ká, èyí tí ó bo ẹ̀dọ̀ àti ìwé méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá tí ó wà lára wọn, ìwọ yóò sì sun wọ́n lórí pẹpẹ.

14. Ṣùgbọ́n fi iná sun ẹran akọ màlúù, awọ rẹ̀ àti ìgbẹ́ rẹ̀ lẹ́yìn òde. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.

15. “Ìwọ yóò sì mú àgbò kan, Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì fi ọwọ́ wọn lé àgbò náà lórí.

Ka pipe ipin Ékísódù 29