Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 5:7-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. “Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ní Ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú ù mi.

8. “Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín ní ìrí ohunkóhun lọ́run tàbí ní ilẹ̀ ní ìṣàlẹ̀ níhìn-ín tàbí nínú omi ní ìṣàlẹ̀.

9. Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ foríbalẹ̀ láti sìn wọ́n. Torí pé èmi Olúwa Ọlọ́run yín Ọlọ́run owú ni mí, tí í fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ baba jẹ ọmọ títí dé ìran kẹ́ta àti ẹ̀kẹ́rin ní ti àwọn tí ó kórìíra mi.

10. Ṣùgbọ́n mo ń fí ìfẹ́ han ẹgbẹẹgbẹ̀rùn-ún ìran àwọn tí ó fẹ́ràn mi, tí ó sì ń pa òfin mi mọ́.

11. “Ẹ má ṣe ṣi orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín lò, torí pé ẹnikẹ́ni tí o bá ṣi orúkọ rẹ̀ lò kì yóò lọ láìjẹ̀bi.

12. “Ẹ kíyèsí ọjọ́ ìsinmi láti pa á mọ́ bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín.

13. Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, kí ẹ ṣe iṣẹ́ ẹ yín pátapáta

14. Ṣùgbọ́n ọjọ́ kéje ni ọjọ́ ìsinmi sí Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà yálà ìwọ tàbí àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin tàbí àwọn ọmọ rẹ obìnrin, tàbí àwọn ẹrú ọkùnrin tàbí ẹrú obìnrin yín tàbí màlúù yín, tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ yín, tàbí èyíkéyìí nínú àwọn ẹran yín, tàbí àwọn àlejò yín, kí àwọn ẹrú-kùnrin àti ẹrú-bìnrin yín le è sinmi, bí i yín.

15. Ẹ rántí pé ẹ ti jẹ́ ẹrú ní Éjíbítì rí, àti pé Olúwa Ọlọ́run yín yọ yín kúrò níbẹ̀ pẹ̀lú agbára ńlá, àti nína ọwọ́ rẹ̀. Torí èyí ni Olúwa Ọlọ́run yín ṣe pàṣẹ fún un yín láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́.

Ka pipe ipin Deutarónómì 5