Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 2:15-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Ọwọ́ Olúwa sì wà lára wọn fún ibi títí gbogbo wọn fi run tan nínú ibùdó.

16. Lẹ́yìn tí ẹni tí ó gbẹ̀yìn pátapáta nínú àwọn jagunjagun àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti kú,

17. Olúwa sọ fún mi pé,

18. “Lónìí ni ẹ̀yin yóò la agbégbé Móábù kọjá ní Árì.

19. Bí ẹ bá dé ọ̀dọ̀ àwọn ará Ámónì, ẹ má ṣe halẹ̀ mọ́ wọn, ẹ kò sì gbọdọ̀ bá wọn jagun, torí pé èmi kì yóò fi àwọn ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ará Ámónì fún un yín ní ìní. Mo ti fi fún àwọn ọmọ Lọ́tì ní ìní.”

20. (A ka ilẹ̀ yìí sí ilẹ̀ àwọn Réfáímù, tí wọ́n ti gbé níbẹ̀ rí, ṣùgbọ́n àwọn ará Ámónì ń pè wọ́n ní Sámúsúmímù.

21. Wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tó lágbára, wọ́n sì pọ̀, wọ́n sì ga gògòrò bí àwọn ará Ánákì. Olúwa run wọn kúrò níwájú àwọn ará Ámónì, tí wọ́n lé wọn jáde tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.

22. Bákan náà ni Olúwa ṣe fún àwọn ọmọ Ísọ̀, tí wọ́n ń gbé ní Séírì, nígbà tí ó pa àwọn ará Hórì run níwájú wọn. Wọ́n lé wọn jáde wọ́n sì ń gbé ní ilẹ̀ wọn títí di òní.

23. Nípa ti àwọn ará Áfì, tí wọ́n ń gbé ní àwọn ìlú kéékèèkéé dé Gásà, àwọn ará Káfórì, tí wọ́n jáde láti Kírétè wá ni ó pa wọ́n run, wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.)

24. “Ẹ gbáradì, kí ẹ sì kọjá odò Ánónì. Kíyèsi, Mo ti fi Ṣíhónì ará Ámórì, ọba Héṣíbónì àti ilẹ̀ rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́. Ẹ bá ilẹ̀ náà jagun kí ẹ sì gbà á.

25. Èmi bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ìbẹ̀rù àti ìfòyà yín sára gbogbo orílẹ̀ èdè lábẹ́ ọ̀run láti òní lọ. Wọn yóò gbọ́ ìròyìn in yín, wọn yóò sì wárìrì, wọn yóò sì wà nínú ìdàmú ọkàn torí i ti yín.”

26. Mo rán àwọn ìránṣẹ́ sí Síhónì láti ihà Kédémótì pẹ̀lú ọ̀rọ̀ àlàáfíà wí pé,

27. “Jẹ́ kí a la ilẹ̀ ẹ yín kọjá. Àwa yóò gba ti òpópónà nìkan. A ko ní yà sọ́tùn-ún tàbí sósì.

28. Ẹ ta oúnjẹ tí a ó jẹ àti omi tí a ó mu fún wa ní iye owó wọn. Kìkì kí ẹ sáà jẹ́ kí a rìn kọjá:

Ka pipe ipin Deutarónómì 2