Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Dáníẹ́lì 10:14-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Ní ìsinsinyí mo wá láti ṣàlàyé ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú, nítorí ìran náà ń sọ nípa ọjọ́ iwájú.”

15. Bí ó sì ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí fún mi, mo sì dorí kodò mo sì dákẹ́.

16. Nígbà náà, ni ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kan ètè mi, mo la ẹnu mi, mo sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ ọ̀rọ̀, mo sọ fún ẹni tí ó dúró níwájú mi, “Ìrònú sì mú mi, nítorí ìran náà, Olúwa mi, n kò sì ní okun.

17. Ǹjẹ́ báwo ni èmi ìránṣẹ́ ẹ̀ rẹ ṣe lè bá ọ sọ̀rọ̀, Olúwa mi? Agbára mi ti lọ, agbára káká ni mo fi ń mí.”

18. Ẹ̀wẹ̀, ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kàn mí, ó sì fún mi ní agbára.

19. Ó sì wí pé, “Má se bẹ̀rù, ìwọ ọkùnrin tí a yàn fẹ́ gidigidi.” Bí ó ti sọ̀rọ̀ fún mi, ara à mí sì le, mo sọ pé, “Má a wí Olúwa mi, níwọ̀n ìgbà tí o ti fún mi ní agbára.”

20. Nígbà náà, ni ó wí pé, “Sé o mọ ìdí tí mo fi tọ̀ ọ́ wá? Láìpẹ́ èmi yóò yípadà lọ bá àwọn ọmọ aládé Páṣíà jà, nígbà tí mo bá lọ àwọn ọmọ aládé Gíríkì yóò wá;

21. ṣùgbọ́n ní àkọ́kọ́, èmi yóò sọ ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé òtítọ́ fún ọ. (Kò sí ẹni tí ó kún mi lọ́wọ́ fún nǹkan wọ̀nyí bí kò ṣe Máíkẹ́lì, ọmọ aládé e yín.

Ka pipe ipin Dáníẹ́lì 10