11. Nígbà náà ni Dáníẹ́lì sọ fún olùṣọ́ tí olórí àwọn ìwẹ̀fà yàn lórí i Dáníẹ́lì, Hananiáyà, Mísáẹ́lì àti Ásáríyà pé,
12. Jọ̀wọ́ dán àwa ìránṣẹ́ rẹ wò fún ọjọ́ mẹ́wàá: Má ṣe fún wa ní ohun kankan, àfi ẹ̀fọ́ láti jẹ àti omi láti mu.
13. Nígbà náà ni kí o fi ìrísí i wa wé ti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí wọ́n ń jẹ oúnjẹ ọba, kí o sì ṣe àwa ìránṣẹ́ rẹ ní ìbámu pẹ̀lú u bí o bá ṣe rí i sí.
14. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì gbà láti dán wọn wò fún ọjọ́ mẹ́wàá.
15. Lẹ́yìn ọjọ́ kẹwàá ara wọn le, wọ́n sì sanra ju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí wọ́n ń jẹ oúnjẹ ọba lọ.
16. Bẹ́ẹ̀ ni olùṣọ́ mú oúnjẹ àdídùn àti wáìnì tí ó yẹ kí wọ́n mu kúrò, ó sì fún wọn ní ẹ̀fọ́ dípò rẹ̀.
17. Ọlọ́run fún àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọ̀nyí ní ìmọ̀ àti òyé nínú un gbogbo onírúurú ìwé àti ẹ̀kọ́ ọ wọn: Dáníẹ́lì sì ní òyé ìran àti àlá ní oríṣìíríṣìí.
18. Ní òpín ìgbà tí ọba dá, pé kí a mú wọn wá sínú ààfin, olórí àwọn ìwẹ̀fà mú wọn wá ṣíwájú ọba Nebukadinésárì.