Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ámósì 7:11-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Nítorí èyí ni ohun ti Ámosì ń sọ:“ ‘Jéróbóámù yóò ti ipa idà kú,Lóótọ́ Ísírẹ́lì yóò lọ sí ìgbèkùn,jìnnà kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’ ”

12. Nígbà náà ni Ámásáyà sọ fún Ámósì pé “Lọ jáde, ìwọ aríran! Padà sí ilẹ̀ àwọn Júdà. Kí o máa jẹun rẹ níbẹ̀ ki o sì sọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ níbẹ̀.

13. Má ṣe sọtẹ́lẹ̀ mọ ni Bẹ́tẹ́lì nítorí ibi mímọ́ ọba ni àti ibi tẹ́ḿpìlì ìjọba rẹ̀.”

14. Ámósì dá Ámásáyà lóhùn pé, “Èmi kì í ṣe wòlíì tàbí àwọn ọmọ wòlíì, ṣùgbọ́n mo jẹ́ olùsọ́-àgùntàn, mo sì ń ṣe ìtọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ síkámórè.

15. Ṣùgbọ́n Olúwa mu mi bí mo ti ń tọ́ agbo ẹran lẹ́yìn, ó sì wí fun mi pé, ‘Lọ sọtẹ́tẹ̀ fun àwọn Ísírẹ́lì ènìyàn mi.’

16. Nítorí náà nísinsin yìí, gbọ ọ̀rọ̀ Olúwa. Ìwọ wí pé,“ ‘Má ṣe sọ àṣọtẹ́lẹ̀ sí Ísírẹ́lìMá ṣì ṣe wàásù sí ilé Ísáákì.’

17. “Nítorí náà, èyí ni ohun ti Olúwa wí:“ ‘Ìyàwó rẹ yóò di paṣángà ni ìlú,àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú.A ó wọn ilẹ̀ rẹ, a ó sì pín inàti ìwọ pẹ̀lú yóò kú ni ilẹ̀ àìmọ́.Ísírẹ́lì yóò sì lọ sí ìgbèkùn,kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’ ”

Ka pipe ipin Ámósì 7