Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ámósì 6:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ará rọ̀ ní Síónìàti ẹ̀yin tí ẹ wà ní abẹ́ ààbò ní òkè Samaríààti ẹ̀yin olókìkí orílẹ̀-èdètí ẹ̀yin ènìyàn Ísírẹ́lì máa ń tọ̀ ọ́ wá

2. Ẹ lọ Kálínì kí ẹ lọ wò óKí ẹ sí tí ibẹ̀ lọ sí Ámátì ìlú ńlá a nì.Kí ẹ sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ Gátì ní ilẹ̀ FílístínìǸjẹ́ wọ́n ha dára ju ìpínlẹ̀ yín méjèèjì lọ?Ǹjẹ́ a ha rí ilẹ̀ tó tóbi ju ti yín lọ bí?

3. Ẹ̀yin sún ọjọ́ ibi síwájú,ẹ sì mú ìjọba òǹrorò súnmọ́ tòòsí

4. Ẹ̀yin sùn lé ibusùn tí a fi eyín erin ṣeẸ sì tan ara sílẹ̀ ni orí àwọn ibùsùnẸ̀yin pa èyí tí o dára nínú àwọn ọ̀dọ́ àgùntàn yín jẹẸ sì ń pa àwọn ọ̀dọ́ màlúù láàrin agbo wọn jẹ

5. Ẹ̀yin ń lo ohun èlò orin bí i DáfídìẸ sì ń ṣe àwọn àpilẹ̀rọ̀ àwọn ohun èlò orin

6. Ẹ̀yín mu wáìnì ẹ̀kún ọpọ́n kanàti ìkunra tí o dára jùlọṢùgbọ́n ẹ̀yin kò káànú ilé Jósẹ́fù tí o di ahoro

Ka pipe ipin Ámósì 6