Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ámósì 5:3-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Èyí ni ohun tí Olúwa ọ̀gá ògo wí:“Ìlú tí ẹgbẹ̀rún alágbára ti jáde,yóò dín ku ọgọ́run ní Ísírẹ́lì.Ìlú tí ọgọ́run alàgbà ti jádeyóò ṣẹ́ku ẹni mẹ́wàá.”

4. Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ilé Ísírẹ́lì:“Wá mi kí o sì yè;

5. Ẹ má ṣe wá Bẹ́tẹ́lì,Ẹ má ṣe lọ sí GílígálìẸ má ṣe rìnrìn àjò lọ sí Bíáṣébà.Nítorí dájúdájú a ó kó Gílígálì ní ìgbèkùnA ó sì sọ Bẹ́tẹ́lì di asán.”

6. Ẹ wá Olúwa, ẹ̀yin yóò sì yè,Kí ó má ba à gbilẹ̀ bí iná ní Jósẹ́fùA sì jó o runBẹ́tẹ́lì kò sì ní rí ẹni tí yóò bomi pa á.

7. Ẹ̀yin tí ẹ̀ sọ òdodo di ìkoròTí ẹ sì gbé olódodo ṣánlẹ̀

8. Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Píláédì àti ÓríónìẸni tí ó sọ òru dúdú di òwúrọ̀Tí ó sọ ọjọ́ dúdú di ìmọ́lẹẸni tí ó wọ́ omi òkun jọpọ̀Tí ó sì rọ̀ wọ́n sí orí ilẹ̀ Olúwa ni orúkọ rẹ̀,

9. Ó fọ́n ìparun sí ìlú olódiTí ó sì sọ àwọn ibùgbé àwọn ọmọ aládé di ahoro

10. Ìwọ kórìíra ẹni tí ń ṣòdì ní ẹnu ibodèó sì ń pẹ̀gàn ẹni tí ń sọ òtítọ́

11. Ìwọ ń tẹ talákà mọ́lẹ̀o ń fi ipá gba ọkà lọ́wọ́ wọnNítorí náà, ìwọ ti fi òkúta tí a gbẹ́ kọ́léṣùgbọ́n ẹ kò sì ní gbé inú wọnNítòótọ́ ìwọ ti gbin ọgbà àjàrà tí ó lẹ́wà.Ìwọ kò ní mu wáìnì inú wọn

12. Nítorí mo mọ iye àìṣedédé rẹmo sì mọ bí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tí tóbi tó.Ìwọ ni olódodo lára, ìwọ sì ń gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀o sì ń fi òtítọ́ du talákà ní ilé ẹjọ́

Ka pipe ipin Ámósì 5