Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ámósì 5:14-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Wá rere, má ṣe wá búburúkí ìwọ ba à le yèNígbà náà ni Olúwa alágbára yóò wà pẹ̀lú ù rẹ.Òun yóò sì wà pẹ̀lú ù rẹ bí ìwọ ṣe wí

15. Kòrìírà búburú kí o sì fẹ́ rereDúró ní orí òtítọ́ ní ilé ẹjọ́Bóyá Olúwa Ọlọ́run alágbárayóò síjú àánú wo ọmọ Jósẹ́fù tó ṣẹ́kù

16. Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run alágbára wí:“Ẹkún yóò wà ní àwọn òpópónàigbe ìnira yóò sì wà ní àwọn gbàgede ìlúA ó kó àwọn àgbẹ̀ jọ láti sunkúnÀti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ láti pohùnréré ẹkún

17. Ìpohùnréré ẹkún yóò wà ní gbogbo ọgbà àjàràNítorí èmi yóò la àárin yín kọjá,”ni Olúwa wí.

18. Ègbé ni fún ìwọ tí ó pẹ́nítorí ọjọ́ Olúwakí ni ìwọ fi pẹ́ fún ọjọ́ Olúwa?Ìmọ́lẹ̀ yóò di òkùnkùn ní ojú ọjọ́

19. Yóò dàbí ọkùnrin tí ó sá láti ẹnu àmọ̀tẹ́kùn.Tí ó padà wá bọ́ sí ẹnu ẹkùnyóò dàbí ẹni tí ó wọ ilé rẹ̀ lọtí ó simi lé ògiri ilé rẹ̀tí ejò sì bù ú ṣán.

20. Ǹjẹ́ ọjọ́ Olúwa kò ha ní ṣókùnkùn dípò kí ó ní ìmọ́lẹ̀?Tí ó sì ṣókùnkùn dúdú láìsí ìmọ́lẹ̀ kankan níbẹ̀

21. “Mo kórìíra, mo kẹ́gàn àwọn àṣè ẹ̀sìn in yínÈmi kò sì ní inú dídùn sí àpèjọ yín

22. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ mú ọrẹ sísun àti ọrẹ ọkà wáÈmi kò ní tẹ́wọ́n gbà wọ́nBí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ mú àṣàyàn ọrẹ àlàáfíà wá.Èmi kò ní náání wọn.

23. Ẹ gbé ariwo orin yín sẹ́yìnÈmi kò ní fetísí ohun èlò orin yín.

24. Jẹ́ kí òtítọ́ ṣàn bí odòàti òdodo bí ìsun tí kò lé è gbẹ

Ka pipe ipin Ámósì 5