Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ámósì 1:4-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Èmi yóò rán iná sí ilé HásáélìÈyí ti yóò jó àwọn ààfin Bẹni-Hádádì run.

5. Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdáàbú Dámásíkù;Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Áfénì runÀti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Bẹti-Édénì.Àwọn ará a Árámù yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kírì,”ni Olúwa wí.

6. Èyí ni ohun tí Olúwa wí:“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gásà,àní nítorí mẹ́rin,Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padàGẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú,ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbékùn.Ó sì tà wọ́n fún Édómù,

7. Èmi yóò rán iná sí ara odi Gásàtí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run

8. Èmi yóò ké àwọn olùgbé Ásódì kúrò.Àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Ákélónì mú.Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ékírónìtítí tí ìyókù Fílístínì yóò fi ṣègbé,”ni Olúwa Ọlọ́run wí.

9. Èyí ni ohun tí Olúwa wí:“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tírèàní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà.Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbékùn fún ÉdómùWọn kò sì nán-án-ní májẹ̀mú ọbàkan,

Ka pipe ipin Ámósì 1