Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 63:1-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ta nì yìí tí ó ń bọ̀ láti Édómù,láti Bósírà, pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ tí osùn ṣe àbàwọ́n fúnTa nì yìí, tí a wọ̀ ní aṣọ ẹ̀yẹ,tí ó ń yan bọ̀ wá nínú ọláńlá agbára rẹ̀?“Èmi ni bí, tí ó ń sọ̀rọ̀ nínú òdodotí ó nípa láti gbàlà.”

2. Èéṣe tí aṣọ yín fi pupagẹ́gẹ́ bí i tàwọn tí ń ṣiṣẹ́ ní ìfúntí?

3. “Èmi nìkan ti dá tẹ ìfúntí wáìnì;láti àwọn orílẹ̀ èdè tí ẹnikẹ́ni kò sì wà pẹ̀lú mi.Mo tẹ̀wọ́n mọ́lẹ̀ ní ìbínú mimo sì tẹ̀ wọ́n rẹ́ ní ìrunú miẹ̀jẹ̀ wọn sì fọ́n sí aṣọ mi,mo sì da àbàwọ́n sí gbogbo aṣọ mi.

4. Nítorí ọjọ́ ẹ̀san wà ní ọkàn miàti pé ọdún ìràpadà mi ti dé

5. Mo wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti ṣe ìrànwọ́.Àyà fò mí pé ẹnikẹ́ni kò ṣèrànwọ́;nítorí náà apá mi ni ó ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún miàti ìrunú mi ni ó gbémiró.

6. Mo tẹ orílẹ̀ èdè mọ́lẹ̀ nínú ìbínú mi;nínú ìrunú mi mo jẹ́ kí wọ́n mumo sì da ẹ̀jẹ̀ wọn sílẹ̀ lórí erùpẹ̀.”

7. Èmi yóò sọ nípa àánú Olúwaìṣe rẹ gbogbo tí ó yẹ kí a yìn ín fún,gẹ́gẹ́ bí ohun tí Olúwa ti ṣe fún wabẹ́ẹ̀ ni, ohun rere gbogbo tí ó ti ṣefún ilé Ísírẹ́lìgẹ́gẹ́ bí àánú àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore rẹ̀.

8. Ó wí pé, “Lótítọ́ ènìyàn mi ni wọ́n,àwọn ọmọ tí kì yóò jẹ́ òpùrọ́ fún mi”;bẹ́ẹ̀ ni, ó sì di Olùgbàlà wọn.

9. Nínú un gbogbo ìpọ́njúu wọn, inú òun pẹ̀lú bàjẹ́àti ańgẹ́lì tí ó wà níwájú rẹ̀ gbà wọ́n là.Nínú Ìfẹ́ àti àánú rẹ̀, ó rà wọ́n padà;ó gbé wọn ṣókè ó sì pọ̀n wọ́nní gbogbo ọjọ́ ìgbà n nì.

10. Ṣíbẹ̀ṣíbẹ̀ wọ́n ṣọ̀tẹ̀wọ́n sì ba Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ nínú jẹ́.Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà ó sì di ọ̀ta wọnòun tìkálára rẹ̀ sì bá wọn jà.

11. Lẹ́yìn náà ni àwọn ènìyàn rẹ̀ rántí ọjọ́ ìgbà n nì,àwọn ọjọ́ Mósè àti àwọn ènìyàn rẹ̀níbo ni ẹni náà wà tí ó mú wọn la òkun já,pẹ̀lú olùṣọ́ àgùntàn agbo ẹran rẹ̀?Níbo ni ẹni náà wà tí ó ránẸ̀mí Mímọ́ rẹ̀ sáàrin wọn,

12. ta ni ó rán ògo apá ti agbára rẹ̀láti wà ní apá ọ̀tún Mósè,ta ni ó pín omi níyà níwájú wọn,láti gba òkìkí ayérayé fún ara rẹ̀,

13. ta ni ó ṣíwájú wọn la àwọn ọ̀gbun nì já?Gẹ́gẹ́ bí ẹṣin ni gbangba ìlú wọn tí kò sì kọṣẹ̀;

Ka pipe ipin Àìsáyà 63