Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 58:10-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. àti bí ẹ̀yin bá ná ara yín bí owó nítorí àwọn tí ebi ń patí ẹ sì tẹ́ ìfẹ́ àwọn tí à ń ni lára lọ́rùn,nígbà náà ni ìmọ́lẹ̀ yín yóò ràn nínú òkùnkùn,àti òru yín yóò dàbí ọ̀ṣán-gangan.

11. Olúwa yóò máa tọ́ ọ yín nígbà gbogbo;òun yóò tẹ́ gbogbo àìní ìn yín lọ́rùn ní ilẹ̀ tí òòrùn ń tan ìmọ́lẹ̀yóò sì fún egungun rẹ lókun.Ìwọ yóò sì dàbí ọgbà tí a bomirin dáadáa,àti bí orísun tí omi rẹ̀ kì í tán.

12. Àwọn ènìyàn rẹ yóò tún ahoro ìṣẹ̀ǹbáyé kọ́wọn yóò sì gbé ìpìlẹ̀ àtijọ́-tijọ́ róa ó sì pè ọ́ ní alátúnṣe ògiri tí ó ti wóàti olùmúbọ̀sípò àwọn òpópónà tí ènìyàn gbé inú un rẹ̀.

13. “Bí ìwọ bá pa ẹṣẹ̀ rẹ mọ́ kúrò nínú bíba ọjọ́-ìsinmi jẹ́,àti síse bí ó ti wù ọ́ ni ọjọ́ mímọ́ mi,bí ìwọ bá pe ọjọ-ìsinmi ní ohun dídùnàti ọjọ́ mímọ́ Olúwa ní ohun ọ̀wọ̀àti bí ìwọ bá bu ọlá fún un láti máa bá ọ̀nà tìrẹ lọàti láti má ṣe bí ó ti wù ọ́ tàbíkí o máa ṣọ̀rọ̀ òòrayè,

14. nígbà náà ni ìwọ yóò ní ayọ̀ nínú Olúwa rẹ,èmi yóò sì jẹ́ kí ìwọ kí ó máa gun ibi gíga ilẹ̀ ayé,àti láti máa jàdídùn ìní tiJákọ́bù baba rẹ.”Ẹnu Olúwa ni ó ti sọ̀rọ̀.

Ka pipe ipin Àìsáyà 58