Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 50:3-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Èmi fi òkùnkùn bo sánmọ̀mo sì fi aṣọ-ọ̀fọ̀ ṣe ìbòrí rẹ̀.”

4. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti fún mi ni ahọ́n tí a fi iṣẹ́ rán,láti mọ àwọn ọ̀rọ̀ tí ó lè gbé àwọn aláàárẹ̀ ró.O jí mi láràárọ̀,o jí etí mi láti gbọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹni tí à ń kọ́.

5. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sí mi ní etí,bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ṣọ̀tẹ̀ rí;Èmi kò sì padà ṣẹ́yìn.

6. Mo sí ẹ̀yìn mi sílẹ̀ fún àwọn tí ó ń nà mí,àti ẹ̀rẹ̀kẹ́ mi fún àwọn tí ń fa irúngbọ̀n mi;Èmi kò fi ojú mi pamọ́kúrò lọ́wọ́ ẹlẹ́yà àti ìyọsùtì sí.

7. Nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ràn mí lọ́wọ́;A kì yóò dójú tìmí.Nítorí náà ni mo ṣe gbé ojú mi ró bí Òkúta akọèmi sì mọ pé, ojú kò ní tì mí.

8. Ẹni tí ó dámiláre wà nítòsí.Ta ni ẹni náà tí yóò fẹ̀ṣùn kàn mí?Jẹ́ kí a kojú ara wa!Ta ni olùfisùn mi?Jẹ́ kí ó kòmí lójú!

9. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó ń ràn mí lọ́wọ́.Ta ni ẹni náà tí yóò dámí lẹ́bi?Gbogbo wọn yóò gbó bí aṣọ;kòkòrò ni yóò sì mú wọn jẹ.

10. Ta ni nínú yín tí ó bẹ̀rù Olúwatí ó sì ń gbọ́ràn sí ìràńṣẹ́ rẹ̀ lẹ́nu?Jẹ́ kí ẹni tí ń rìn ní òkùnkùntí kò ní ìmọ́lẹ̀,kí ó gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwakí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run rẹ̀.

Ka pipe ipin Àìsáyà 50