Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 5:1-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èmi yóò kọrin fún ẹni tí mo fẹ́rànorin kan nípa ọgbà-àjàrà rẹ̀;Olùfẹ́ẹ̀ mi ní ọgbà-àjàrà kanní ẹ̀gbẹ́ òkè ẹlẹ́tù lójú.

2. Ó tu ilẹ̀ rẹ̀, ó ṣa òkúta ibẹ̀ kúròó sì gbin àyànfẹ́ àjàrà síi.Ó kọ́ ilé-ìṣọ́ sí inú un rẹ̀ó sì ṣe ìfúntí kan ṣíbẹ̀ pẹ̀lú.Lẹ́yìn náà, ó ń retí èso àjàrà dáradára,ṣùgbọn èṣo búburú ni ó ti ibẹ̀ wá.

3. “Ní ìsinsin yìí ẹ̀yín olùgbé Jérúsálẹ́mùàti ẹ̀yin ènìyàn Júdàẹ ṣe ìdájọ́ láàrin èmi àtiọgbà àjàrà mi.

4. Kín ni ó kù tí n ò bá tún ṣe sí ọgbà àjàrà mi.Ju èyí tí mo ti ṣe lọ?Nígbà tí mo ń wá èso dáradára,èéṣe tí ó fi ṣo kíkan?

5. Ní ìsinsìn yìí, èmi yóò sọ fún ọohun tí n ó ṣe sí ọgbà-àjàrà mi:Èmi yóò gé igi inú un rẹ̀ kúrò,a ó sì pa á run,Èmi yóò wó ògiri rẹ̀ lulẹ̀yóò sì di ìtẹ̀mọ́lẹ̀.

6. Èmi yóò sì sọ ọ́ di ahoroláì kọ ọ́ láì rò ó,ẹ̀wọ̀n àti ẹ̀gún ni yóò hù níbẹ̀.Èmi yóò sì pàṣẹ fún kùrukùruláti má ṣe rọ̀jò sóríi rẹ̀.”

7. Ọgbà-àjàrà Olúwa àwọn ọmọ-ogunni ilé Ísírẹ́lìàwọn ọkùnrin Júdàsì ni àyànfẹ́ ọgbà rẹ̀.Ó retí ìdájọ́ ẹ̀tọ́ ṣùgbọn, ìtàjẹ̀sílẹ̀ ni ó rí,Òun ń retí òdodo ṣùgbọ́n ó gbọ ẹkún ìpayínkeke.

8. Ègbé ni fún àwọn tí ń kọ́lé mọ́létí ó sì ń ra ilẹ̀ mọ́lẹ̀tó bẹ́ẹ̀ tí ààyè kò ṣẹ́kùtí ó sì nìkan gbé lórí ilẹ̀.

9. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ ọ́ sími létí“Ó dájú pé àwọn ilé ńlá ńláyóò di ahoro, àwọn ilé dára dára yóò wà láìní olùgbé.

10. Ọgbà-àjàrà sarè oko mẹwàá yóò múìkòkò wáìnì kan wá,nígbà tí òṣùwọ̀n hómérì kan yóò múagbọ̀n irúgbin kan wá.”

11. Ègbé ni fún àwọn tí wọ́n dìdení kùtùkùtù òwúrọ̀láti lépa ọtí líle,tí wọ́n sì mu ún títí alẹ́ fi lẹ́títí wọ́n fi gbinájẹ pẹ̀lú wáìnì.

Ka pipe ipin Àìsáyà 5