Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 47:1-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Ṣọ̀kalẹ̀, jókòó nínú eruku,wúndíá ọmọbìnrin Bábílónì;jókòó ní ilẹ̀ẹ́lẹ̀ láìsí ìtẹ́,ọmọbìnrin àwọn ará Bábílónì.A kì yóò pè ọ́ ní aláìlókun àti ẹlẹgẹ́ mọ́.

2. Mú òkúta-ọlọ kí o sì lọ ìyẹ̀fun;mú ìbòjú ù rẹ kúrò.Ká yẹ̀rì rẹ sókè, kí o hó ẹṣẹ̀ rẹ sílẹ̀,kí o sì la inú odò lọ.

3. Ìhòòhò rẹ ni a ó fihàn sítaàti ìtìjú rẹ ni a ó sí sílẹ̀.Èmi yóò sì gba ẹ̀ṣan;Èmi kì yóò sì dá ẹnìkan sí.”

4. Olùràpadà wa Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀òun ni Ẹni-Mímọ́ Ísírẹ́lì.

5. “Jókòó ní ìdákẹ́jẹ́ẹ́, lọ sínú òkùnkùn,ọmọbìnrin àwọn ará Bábílónì;a kì yóò pè ọ́ ní ọbabìnrinàwọn ilẹ̀-ọba mọ́.

6. Inú bí mi sí àwọn ènìyàn mití mo sì ba ogún mi jẹ́;Mo fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́,Ìwọ kò sì síjú àánú wò wọ́n.Lórí àwọn arúgbó pẹ̀lúní o gbé àjàgà tí ó wúwo lé.

7. Ìwọ wí pé, ‘Èmi yóò tẹ̀ṣíwájú títí láé—ọba-bìnrin ayérayé!’Ṣùgbọ́n ìwọ kò kíyèsí nǹkan wọ̀nyítàbí kí o ronú nípa ohun tí ó lè ṣẹlẹ̀.

8. “Nísinsìn yìí, tẹ́tísílẹ̀, ìwọ oníwọ̀ra ẹ̀dátí o kẹ̀tẹ̀ǹfẹ̀ nínú ààbò rẹtí o sì ń sọ fún ara rẹ pé,‘Èmi ni, kò sì sí ẹlòmìíràn lẹ́yìn mi.Èmi kì yóò di opótàbí kí n pàdánù àwọn ọmọ.’

9. Méjèèjì yìí ni yóò wá sóríì rẹláìpẹ́ jọjọ, ní ọjọ́ kan náà:pípàdánù ọmọ àti dídi opó.Wọn yóò wá sóríì rẹ ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́,pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ìṣe oṣó rẹàti àwọn èpè rẹ tí kì í ṣélẹ̀.

10. Ìwọ ti ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ìwà ìkà rẹó sì ti wí pé, ‘kò sí ẹni tí ó rí mi?’Ọgbọ́n àti òye rẹ ti sì ọ́ lọ́nànígbà tí o wí fún ara rẹ pé,‘Èmi ni, kò sí ẹlòmìíràn lẹ́yìn mi.’

11. Ìparun yóò dé bá ọbẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò mọ ọ̀nà láti ré e kúrò.Àjálù kan yóò ṣubú lù ọ́tí o kì yóò le è fi ètùtù ré kúrò;òfò kan tí o kò le ròtì niyóò wá lójijì sí oríì rẹ.

12. “Tẹ̀ṣíwájú nígbà náà, pẹ̀lú àfọ̀ṣẹ rẹàti pẹ̀lú ìwà oṣó rẹ gbogbo,tí o ti ń ṣiṣẹ́ fún láti ìgbà èwe rẹ wá.Bóyá o le è ṣàṣeyọrí,bóyá o le è dá rúgúdù sílẹ̀.

13. Gbogbo ìmọ̀ràn tí o ti gbà nió ti sọ ọ́ di akúrẹtẹ̀!Jẹ́ kí àwọn awòràwọ̀ rẹ bọ́ síwájú,Àwọn awòràwọ̀ tí wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀láti oṣù dé oṣù,jẹ́ kí wọ́n gbà ọ́ lọ́wọ́ ohun tí ó ń bọ̀ wá bá ọ.

Ka pipe ipin Àìsáyà 47