Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 45:11-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. “Ohun tí Olúwa wí nìyìíẸni Mímọ́ Ísírẹ́lì, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀:Nípa ohun tí ó ń bọ̀,ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi,tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?

12. Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayétí ó sì da ọmọnìyàn sóríi rẹ̀.Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀runmo sì kó àwọn agbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta

13. Èmi yóò gbé Kírúsì ṣókè nínú òdodo mi:Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́.Òun yóò tún ìlú mi kọ́yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀,ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan,ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”

14. Ohun tí Olúwa wí nìyìí:“Àwọn èròjà ilẹ̀ Éjíbítì àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kúṣì,àti àwọn Ṣábíáṣì—wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹwọn yóò sì jẹ́ tìrẹ;wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn,wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́.Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀,wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé,‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì sí ẹlòmìíràn;kò sí ọlọ́run mìíràn.’ ”

15. Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́,Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Ísírẹ́lì

16. Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tìwọn yóò sì kan àbùkù;gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.

17. Ṣùgbọ́n Ísírẹ́lì ni a ó gbàlà láti ọwọ́ OlúwaPẹ̀lú ìgbàlà ayérayé;a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójú tì yín,títí ayé àìnípẹ̀kun.

18. Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí—ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run,Òun ni Ọlọ́run;ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé,Òun ló ṣe é;Òun kò dá a láti wà lófo,ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀—Òun wí pé:“Èmi ni Olúwa,kò sì sí ẹlòmìíràn.

Ka pipe ipin Àìsáyà 45