Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Sámúẹ́lì 15:26-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. Ṣùgbọ́n bí òun bá sì wí pé, ‘Èmi kò ní inú dídùn sí ọ,’ wò ó, èmi nì yìí, jẹ́ kí òun ó ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí o ti tọ́ ní ojú rẹ̀.”

27. Ọba sì wí fún Sádókù àlùfáà pé, “Aríran ha kọ́ ni ọ́? Padà sí ìlú ní àlàáfíà, àti àwọn ọmọ rẹ méjèèjì pẹ̀lú rẹ, Áhímásì ọmọ rẹ, àti Jónátanì ọmọ Ábíátárì.

28. Wò ó, èmi ó dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ijù náà, títí ọ̀rọ̀ ó fi ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá láti sọ fún mi.”

29. Sádókù àti Ábíátarì sì gbé àpótí-ẹ̀rí Ọlọ́run padà sí Jérúsálẹ́mù: wọ́n sì gbé ibẹ̀.

30. Dáfídì sì ń gòkè lọ ní òkè igi ólífì, o sì ń sunkun bí ó ti ń gòkè lọ, ó sì bo orí rẹ̀, ó ń lọ láìní bàtà ní ẹṣẹ̀: gbogbo ènìyàn tí o wà lọ́dọ̀ rẹ̀, olúkúlùkù ọkùnrin sì bo orí rẹ̀, wọ́n sì ń gòkè lọ, wọ́n ń sunkún bí wọ́n ti ń gòkè lọ.

31. Ẹnìkan sì sọ fún Dáfídì pé, “Áhítófélì wà nínú àwọn asọ̀tẹ̀ pẹ̀lù Ábúsálómù.” Dáfídì sì wí pé, “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, sọ ìmọ̀ Áhítófélì di asán.”

32. Ó sì ṣe, Dáfídì dé orí òkè, níbi tí ó gbé wólẹ̀ sin Ọlọ́run, sì wò ó, Húsáì ará Áríkà sì wá láti pàdé rẹ̀ pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ yíya, àti erùpẹ̀, lórí rẹ̀.

33. Dáfídì sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá bá mi kọjá, ìwọ ó sì jẹ́ ìdíwọ́ fún mi.

34. Bí ìwọ bá sì padà sí ìlú, tí o sì wí fún Ábúsálómù pé, ‘Èmi ó ṣe ìránṣẹ́ rẹ ọba, gẹ́gẹ́ bí èmi ti ṣe ìránṣẹ́ baba rẹ nígbà àtíjọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó sì jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ nísínsinyìí,’ kí ìwọ sì bá ìmọ̀ Áhítófélì jẹ́.

35. Ṣé Sádókù àti Ábíátarì àwọn àlùfáà wà níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀? Yóò sì ṣe, ohunkóhùn tí ìwọ bá gbọ́ láti ilé ọba wá, ìwọ ó sì sọ fún Sádókù àti Ábíátarì àwọn àlùfáà.

36. Wò ó, àwọn ọmọ wọn méjèèjì sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú wọn, Áhímásì ọmọ Sádókù, àti Jónátánì ọmọ Ábíátárì; láti ọwọ́ wọn ni ẹ̀yín ó sì rán ohùnkóhun tí ẹ̀yín bá gbọ́ sí mi.”

Ka pipe ipin 2 Sámúẹ́lì 15