Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 7:11-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Àwọn aṣọ́bodè náà pariwo ìròyìn náà, wọ́n sì sọ nínú ààfin.

12. Ọba sì dìde ní ùru ó sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Èmi yóò ṣọ fún yín ohun tí àwọn ará Ṣíríà tí ṣe fún wa. Wọ́n mọ̀ wí pé ebi ń pa wá; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ti kúrò ni ibùdó láti sá pamọ́ sí ẹ̀gbẹ́ ilé, wọ́n rò wí pé, ‘Wọn yóò jáde lóòtọ́, nígbà náà àwa yóò mú wọn ní ààyè àwa yóò yí wọ inú ìlú lọ.’ ”

13. Ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ dáhùn pé, “Mú ọkùnrin díẹ̀ mú márùnún lára àwọn ẹsin tí wọ́n fi sílẹ̀ nínú ìlú. Ìwà wọn yóò dà bí gbogbo àwọn ará Ísírẹ́lì tí ó kù níbẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni, wọn yóò dà bí gbogbo àwọn Ísírẹ́lì, yìí nìkan tí a run. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ jẹ́ kí a rán wọn lọ láti lọ wo ohun tí ó ṣẹlẹ̀.”

14. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yan kẹ̀kẹ́ méjì pẹ̀lú ẹsin wọn, ọba sì ránsẹ́ tọ ogun àwọn ará Síríà lẹ́yìn ó pàṣẹ fún àwọn awakọ̀ pé, “Ẹ lọ kí e lọ wo ohun tí ó ṣẹlẹ̀.”

15. Wọ́n sì tẹ̀lé wọn títí dé Jọ́dánì, wọ́n sì rí gbogbo ọ̀nà kún fún agbádá pẹ̀lú ohun èlò tí ará àwọn Ṣíríà gbé sọnù ní yàrá wọn. Ìránsẹ́ náà padà ó sì wá sọ fún ọba.

16. Nígbà náà àwọn ènìyàn jáde lọ ìkógun ní ibùdó àwọn ará Ṣíríà. Bẹ́ẹ̀ ni òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kan ni wọ́n tà fún Sẹ́kẹ́lì kan, àti òsùnwọ̀n báálì méjì ní Ṣékélì kan, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.

17. Nísìn yìí ọba sì mú ìjòyè náà lórí ẹni tí ó fi ọwọ́ ara rẹ̀ tì ní ìkáwọ́ ẹnu ibodè, àwọn ènìyàn sì tẹ̀ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ẹnu ibodè. Ó sì kú, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti ṣọ tẹ́lẹ̀ nígbà tí ọba sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.

18. Ó sì ti sẹlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ènìyan Ọlọ́run ti ṣọ fún ọba: “Ní àsìkò yìí ní ọ̀la, òsùnwọ̀n ìyẹ̀fun ni a ó ta nì Ṣékélì kan àti òsùnwọ̀n méjì báálì ní Ṣékélì kan ní ẹnu ọ̀nà ibodè Ṣamáríà.”

19. Ìjòyè náà ti wí fún ènìyàn Ọlọ́run pé, “Wò ó, kó dà ti Olúwa bá sí fèrèsé ní ọ̀run, ṣé èyí lè ṣẹlẹ̀?” Ènìyàn Ọlọ́run sì ti dáhùn pé, “kìkì ojú rẹ ni ìwọ yóò fi rí i, Ṣùgbọ́n ìwọ kò ní jẹ ọ̀kan kan lára rẹ̀.”

Ka pipe ipin 2 Ọba 7