Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 7:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èlíṣà wí pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: Ní àsìkò yìí ní ọ̀la, a ó ta òṣùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúná kan ní ṣékélì kan àti méjì òṣùwọ̀n ọkà fún ṣékélì kan ní ẹnu bodè Samáríà.”

2. Ìjòyè kan ẹni tí ọwọ́ ọba ń fi ara tì dáhùn wí fún ènìyàn Ọlọ́run pé, “Ẹ wòó, tí Olúwa bá tilẹ̀ sí fèrèsé ọ̀run sílẹ̀, ṣé èyí lè rí bẹ́ẹ̀?”“Ìwọ yóò rí i pẹ̀lú ojú rẹ,” Èlíṣà dáhùn, “ṣùgbọ́n ìwọ kò ní jẹ nǹkankan lára rẹ̀!”

3. Nísinsìn yìí àwọn ọkùnrin mẹ́rin kan wà pẹ̀lú ẹ̀tẹ̀ ní ẹnu àbáwọlé ibodè ìlú. Wọ́n wí fún olúkúlùkù pé, “kí ni ó dé tí àwa yóò fi jókòó síbí títí àwa yóò fi kú?

4. Tí àwa bá wí pé, ‘Àwa lọ sí ìlú, ìyàn wà níbẹ̀,’ àwa yóò sì kú. Tí àwa bá dúró níbí, a máa kú, ǹjẹ́ Nísinsìnyí ẹ jẹ́ kí a lọ sí ibùdó ti àwọn ará Síríà kí àwa kí ó sì tẹríba. Bí wọ́n bá dá wa sí, àwa yóò yè, tí wọ́n bá sì pa wá, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò kú.”

5. Ní àfẹ̀mójúmọ́ wọ́n dìde wọ́n sì lọ sí ibùdó àwọn ará Síríà. Nígbà tí wọ́n dé ẹ̀gbẹ́ ibùdó náà, kò sí ọkùnrin kan níbẹ̀,

Ka pipe ipin 2 Ọba 7