Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 23:30-37 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

30. Ìránṣẹ́ Jòṣíáyà gbé ara rẹ̀ wá nínú kẹ̀kẹ́ láti Mègídò sí Jérúsálẹ́mù ó sì sin ín sínú iṣà òkú rẹ̀. Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú Jéhóáhásì ọmọ Jòṣíáyà. Ó fi àmì òróró yàn án, ó sì ṣe é ní ọba ní ipò bàbá a rẹ̀.

31. Jéhóáhásì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́talélógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jọba ní Jérúsálẹ́mù fún oṣù mẹ́ta. Orúkọ ìyá a rẹ̀ a máa jẹ́ Hámútalì ọmọbìnrin Jeremíáyà; ó wá láti Líbínánì.

32. Ó ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.

33. Fáráò Nékó sì fi sí inú ìdè ní Ríbílà ní ilẹ̀ Hámátì, kí ó má ba à lè jọba ní Jérúsálẹ́mù. Ó sì tan Júdà jẹ fun iye ìwọ̀n ẹgbẹ̀rin talẹ́ntì wúrà kan.

34. Fáráò Nékò ṣe Élíákímù ọmọ Jòṣíàh ní ọba ní ipò baba rẹ̀ Jòsáyà. Ó sì yí orúkọ Élíákímù padà sí Jéhóíákímù. Ṣùgbọ́n ó mú Jéhóáhásì, ó sì gbéé lọ sí Éjíbítì, níbẹ̀ ni ó sì kú.

35. Jéhóíákímù sì san fún Fáráò Nékónì fàdákà àti wúrà tí ó béèrè. Lati ṣe bẹ́ẹ̀, ó bu owó òde fún ilẹ̀ náà láti san, ó fi agbára gba fàdákà àti wúrà láti ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà ní ìbámu pẹ̀lú iye tí a pín.

36. Jéhóíákímù jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jọba ní Jérúsálẹ́mù fún ọdún mọ́kànlá orúkọ ìyá a rẹ̀ a máa jẹ́ Ṣébídà ọmọbìnrin Pédáíáyà ó wá láti Rúmà.

37. Ó sì ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.

Ka pipe ipin 2 Ọba 23