Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 23:24-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Síwájú sí, Jòsíáyà sì lé àwọn oṣó àti àwọn ẹ̀mí ní àwọn ìdílé, àti àwọn òrìṣà àti gbogbo àwọn nǹkan ìríra tí a rí ní Júdà àti ní Jérúsálẹ́mù. Èyí ni ó ṣe kí ó le è mú ọ̀rọ̀ òfin náà ṣe ní ti òfin tí a kọ sínú ìwé tí Hílíkíyà àlùfáà ti rí nínú ilé Olúwa.

25. Kò sì sí ọba kankan níwájú tàbí lẹ́yìn Jóṣíáyà tí ó dàbí rẹ̀, tí ó yí padà sí olúwa tinútinú àti gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe tọkàntọkàn pẹ̀lú gbogbo ẹ̀mí i rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo agbára rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin Móṣè.

26. Bí ó ti wù kí ó rí Olúwa kò yípadà kúrò nínú ìmúná ìbínú ńlá rẹ̀ tí ó jó sí Júdà, nítorí gbogbo èyí tí Mánásè ti ṣe láti mú un bínú.

27. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí pé, “Èmi yóò mú Júdà kúrò pẹ̀lú níwájú mi, bí mo ti mú Ísírẹ́lì, èmi yóò sì kó Jérúsálẹ́mù, ìlú ńlá tí mo yàn àti ilé Olúwa yìí, nípa èyí tí mo sọ, ‘Níbẹ̀ ni orúkọ mi yóò wà?’ ”

28. Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Jòṣíà, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Júdà?

29. Nígbà tí Jòṣíà jẹ́ ọba, Fáráò Nékò ọba Éjíbítì gòkè lọ sí odò Yúfúrátè láti lọ ran ọba Ásíríà lọ́wọ́. Ọba Jòṣíáyà jáde lọ láti lọ bá a pàdé lójú ogun ṣùgbọ́n Nékò dojúkọ ọ́, ó sì pa á ní Mégídò.

Ka pipe ipin 2 Ọba 23