Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 18:13-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Ní ọdún kẹrìnlá tí Heṣekáyà jọba, Ṣenakérúbù ọba Ásíríà kọlu gbogbo ìlú olódi ti Júdà ó sì pa wọ́n run.

14. Bẹ́ẹ̀ ni Heṣekáyà ọba Júdà rán oníṣẹ́ yìí sí ọba Áṣíríà ní Lákísì, “Mo ti mú ìṣe ohun tí kò dára kúrò lọ́dọ̀ mi, èmi yóò sì san ohunkóhun tí ìwọ bá béèrè lọ́wọ́ mi.” Ọba bu ọ̀ọ́dúnrún talẹ́ntì fàdákà àti ọgbọ̀n talẹ́ntì wúrà.

15. Heṣekáyà fún un ní gbogbo fàdákà tí wọ́n rí nínú ilé Olúwa àti nínú ilé ìṣúra ọba.

16. Ní àkókò yìí Heṣekáyà ọba Júdà ké wúrà tí ó wà ní ẹnu ìlẹ̀kùn ilé Olúwa, kúrò àti ti òpó tí Heṣekáyà ọba Júdà ti gbéró ó sì fi fún ọba Ásíríà.

17. Ọba Ásíríà rán alákòóṣo gíga jùlọ, ìjòyè pàtàkì àti àwọn adarí pápá pẹ̀lú àwọn ọmọ ogun tí ó pọ̀, láti Lákísì sí ọba Heṣekáyà ní Jérúsálẹ́mù. Wọ́n wá sí òkè Jérúsálẹ́mù wọ́n sì dúró ní etí ìdarí omi àbàtà òkè, ní ojú ọ̀nà tó lọ sí òpópó pápá Alágbàfọ̀.

18. Wọ́n sì pe ọba; àti Eliákímù ọmọ Hílíkíyà ẹni tí í ṣe ilé olùtọ́jú, Ṣébínà akọ̀wé, àti Jóà ọmọkùnrin Ásáfù tí ó jẹ́ akọ̀wé ìrántí jáde pẹ̀lú wọn.

19. Olùdarí pápá wí fún wọn pé, “Sọ fún Heṣekáyà pé:“ ‘Èyí ni ohun tí ọba ńlá, ọba Ásíríà sọ: Lórí kí ni ìwọ ń dá ìgbóyà rẹ̀ yìí?

20. Ìwọ wí pé ìwọ ni ẹ̀tà àti ti ogun alágbára ṣùgbọ́n ìwọ sọ̀rọ̀ òfìfo nìkan, lórí ta ni ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé tí ìwọ fi ń ṣe ọ̀tẹ̀ sí mi?

Ka pipe ipin 2 Ọba 18