Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 13:16-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. “Mú ọrun ní ọwọ́ rẹ.” Ó wí fún ọba Ísírẹ́lì. Nígbà tí ó ti mú u, Èlíṣà mú ọwọ́ rẹ̀ lé ọwọ́ ọba.

17. “Ṣí fèrèsé apá ìlà oòrùn,” ó wí, pẹ̀lú ó sì ṣéé: “Ta á!” Èlíṣà wí, ó sì ta á. “Ọfà ìṣẹ́gun Olúwa; ọfà ìṣẹ́gun lórí Ṣíríà!” Èlíṣà kéde. “Ìwọ yóò pa àwọn ará Ṣíríà run pátapáta ní Áfékì.”

18. Nígbà náà ó wí pé, “Mú àwọn ọfà náà,” ọba sì mú wọn. Èlíṣà wí fún un pé, “Lu ilẹ̀.” Ó lù ú lẹ́ẹ̀mẹ́ta, ó sì dáwọ́ dúró.

19. Ènìyàn Ọlọ́run sì bínú sí i, ó sì wí pé, “Ìwọ kò bá ti lu ilẹ̀ ní ẹẹ̀marùn-ún tàbí ní ẹ̀ẹ̀mẹfà; Nígbà náà, ìwọ kò bá ti ṣẹ́gun Ṣíríà àti pa á run pátapáta ṣùgbọ́n Nísinsìn yìí ìwọ yóò ṣẹ́gun rẹ̀ ní ẹ̀mẹ́ta péré.”

20. Èlíṣà kú a sì sin ín.Ẹgbẹ́ Àwọn ará Móábù máa ń wọ orílẹ̀ èdè ní gbogbo àmọ́dún.

21. Bí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kan ti ń sin òkú ọkùnrin kan, lójijì wọ́n rí ẹgbẹ́ àwọn oníjadì: Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ju òkú ọkùnrin náà sínú ibojì Èlíṣà. Nígbà tí ara ọkùnrin náà kan egungun Èlíṣà, ó padà wá sí ayé, ó sì dúró ní ẹsẹ̀ rẹ̀.

22. Hásáélì ọba Ṣíríà ni Ísírẹ́lì lára ní gbogbo àkókò tí Jéhóáhásì fi jọba.

23. Ṣùgbọ́n Olúwa ṣàánú fún wọn ó sì ní ìyọ́nú, ó sì fiyèsí wọn nítorí májẹ̀mú rẹ̀ pẹ̀lú Ábúráhámù, Ísákì àti Jákọ́bù. Títí di ọjọ́ òní, kì í ṣe ìfẹ́ inú rẹ̀ láti pa wọ́n run tàbí lé wọn lọ níwájú rẹ̀.

Ka pipe ipin 2 Ọba 13