Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 32:1-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Lẹ́yìn gbogbo èyí ti Heṣekíà ti fi otítọ́ se, Senakéríbù ọba Ásíríà wá ó sì gbógun ti Júdà. Ó gbógun ti àwọn ìlú ààbò, ó ń ronú láti ṣẹ́gun wọn fún ararẹ̀.

2. Nígbà tí Heṣekáyà rí i pé Senakérébù ti wá, àti pé ó fẹ́ láti dá ogun sílẹ̀ lóri Jérúsálẹ́mù,

3. Ó gbèrò pẹ̀lu àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ tí wọ́n fẹ́rẹ̀ ẹ́ di orísun omi ní ìta ìlú ńlá, wọ́n sì ràn án lọ́wọ́.

4. Ọ̀pọ̀ ogun ọkùnrin péjọ, wọ́n sì dí gbogbo àwọn orísun àti àwọn omi tó ń ṣàn tí ó ń sàn gba ti ilẹ̀ naà. “Kí ni ó dé tí àwọn ọba Ásíríà fi wá tí wọ́n sì rí ọ̀pọ̀ omi?” Wọ́n wí.

5. Nígbà náà ó ṣiṣẹ́ gidigidi ní títún gbogbo ìtorí ara ògiri tí ó ti bàjẹ́ ṣe, ó sì ń kọ́ àwọn ilé iṣẹ́ gíga sókè rẹ̀. Ó kọ́ ògiri mìíràn sí ìta ìyẹn. Ó sì rán ibi ìfẹ̀yìntì lọ́wọ́ pẹ̀lú ibi ìtẹ́jú ilé níti ìlú ńlá Dáfídì. Ó ṣe ọ̀pọ̀ iye ohun ìjà àti àwọn àpáta.

6. Ó yan àwọn ìjòyè ológun sórí àwọn ènìyàn, ó sì pèwọ́n jọ, níwájú rẹ̀ ní ìbámu ní ìlú ńlá ti Dáfídì. Ó sì ki wọ́n láyà pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí:

7. “Ẹ jẹ́ alágbára, àti kí ẹ sì ní ìgboyà. Ẹ má se bẹ̀rù tàbí ní ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn nítorí tí ọba Ásíríà àti ọ̀pọ̀ ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí agbára ńlá wà pẹ̀lú wa ju òun lọ.

8. Agbára ẹran ara nìkan ni ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ṣùgbọ́n, pẹ̀lú wa ni Ọlọ́run láti ràn wá lọ́wọ́ àti láti ja ìjà wa.” Àwọn ènìyàn sì ní ìgboyà láti ara ohun tí Hesekía ọba Júdà wí.

9. Lẹ́yìn ìgbà tí Senakéríbù ọba Ásíríà àti gbogbo àwọn ogun rẹ̀ ń gbógun sí Lákíṣì. Ó rán àwọn ìjòyè rẹ̀ sí Jérúsálẹ́mù pẹ̀lú iṣẹ́ yí fún Heṣekáyà ọba Júdà àti fún gbogbo àwọn ènìyàn Júdà tí ó wà níbẹ̀:

10. “Èyí ni ohun tí Senakéríbù ọba Ásíríà wí: Lórí kí ni ẹ̀yin gbé ìgbẹ́kẹ̀lé yín lé, tí ẹ̀yin fi dúró sí Jérúsálẹ́mù lábẹ́ ìgbógun sí?

11. Nígbà tí Heṣekáyà wí pé ‘Olúwa Ọlọ́run wa yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ ọba Ásíríà, ó ń sì yín tọ́ sọ́nà, kí ẹ bá lè kú fún ebi àti òǹgbẹ.’

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 32