Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 22:36-41 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

36. A sì kéde la ibùdó já ní àkókò ìwọ̀ oòrùn wí pé, “Olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀ àti olúkúlùkù sí ilẹ̀ rẹ̀!”

37. Bẹ́ẹ̀ ni ọba kú, a sì gbé e wá sí Samáríà, wọ́n sì sin ín ní Samáríà.

38. Wọ́n sì wẹ kẹ̀kẹ́ náà ní adágún Samáríà, àwọn ajá sì lá ẹ̀jẹ̀ rè, àwọn àgbérè sì wẹ ara wọn nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti sọ.

39. Níti ìyókù ìṣe Áhábù, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, àti ilé eyin-erin tí ó kọ́, àti gbogbo ìlú tí ó tẹ̀dó, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Ísírẹ́lì?

40. Áhábù sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Áhásáyà ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.

41. Jèhósáfátì ọmọ Áṣà, sì bẹ̀rẹ̀ sí ní jọba lórí Júdà ní ọdún kẹrin Áhábù ọba Ísírẹ́lì.

Ka pipe ipin 1 Ọba 22