Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 19:15-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀nà tí ìwọ ti wá, kí o sì lọ sí ihà Dámásíkù. Nígbà tí ìwọ bá dé ibẹ̀, fi òróró yan Hásáélì ní ọba lórí Árámù.

16. Tún fi òróró yan Jéhù ọmọ Nímísì ní ọba lórí Ísírẹ́lì, àti kí o fi òróró yan Èlíṣà ọmọ Sáfátì, ará Ábélí-Méhólà ní wòlíì ní ipò rẹ.

17. Jéhù yóò pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Hásáélì, Èlíṣà yóò sì pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Jéhù.

18. Ṣíbẹ̀, Èmi ti pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàarin (700) ènìyàn mọ́ fún ara mi ní Ísírẹ́lì, àní gbogbo eékún tí kò ì tíì kúnlẹ̀ fún òrìṣà Báálì, àti gbogbo ẹnu tí kò ì tí ì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.”

19. Bẹ́ẹ̀ ni Èlíjà lọ kúrò níbẹ̀, ó sì rí Èlíṣà ọmọ Sáfátì. Ó ń fi àjàgà màlúù méjìlá tulẹ̀ níwájú rẹ̀, àti òun náà níwájú ìkéjìlá. Èlíjà sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì da agbádá rẹ̀ bò ó.

20. Nígbà náà ni Èlíṣà sì fi àwọn màlúù sílẹ̀, ó sì ṣáré tọ Èlíjà lẹ́yìn. Ó wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí èmi lọ fi ẹnu ko baba àti ìyá mi ní ẹnu. Nígbà náà ni èmi yóò tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.”Èlíjà sì dáhùn wí pé, “Padà ṣẹ́yìn, kí ni mo fi ṣe ọ́?”

21. Èlíṣà sì fi í sílẹ̀, ó padà ṣẹ́yìn. Ó sì mú àjàgà màlúù rẹ, ó sì pa wọ́n. Ó sì fi ohun-èlò àwọn màlúù náà bọ́ ẹran wọn, ó sì fi fún àwọn ènìyàn, wọ́n sì jẹ. Nígbà náà ni ó sì dìde láti tọ Èlíjà lẹ́yìn, ó sì ṣe ìránṣẹ́ fún un.

Ka pipe ipin 1 Ọba 19